< Psalms 91 >

1 Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
Celui qui habite dans la retraite du Très-Haut Repose à l'ombre du Tout-Puissant.
2 Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
Je dis à l'Éternel: «Tu es mon refuge et ma forteresse, Mon Dieu en qui je mets ma confiance!»
3 Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
C'est lui qui te délivrera du filet de l'oiseleur Et de la peste meurtrière.
4 Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
Il te couvrira de ses ailes. Et sous sa protection tu trouveras un refuge; Sa fidélité sera ton bouclier protecteur.
5 Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
Tu ne craindras ni les terreurs de la nuit. Ni la flèche qui vole pendant le jour,
6 tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
Ni la peste qui se glisse à travers les ténèbres, Ni la mortalité qui sévit en plein midi.
7 Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Quand il tomberait mille hommes à ton côté Et dix mille à ta droite. Tu ne serais pas atteint.
8 Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
Mais toi, tu contempleras de tes yeux Et tu verras le châtiment des méchants.
9 Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
Oui, tu es mon refuge, ô Éternel! Tu as pris le Très-Haut pour ton asile.
10 Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
Aucun mal ne t'atteindra; Aucun fléau n'approchera de ta tente.
11 Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
Car il ordonnera à ses anges De te garder dans toutes tes entreprises.
12 wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
Ils te porteront sur leurs mains, De peur que ton pied ne heurte contre une pierre.
13 Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Tu marcheras sur le lion et sur l'aspic; Tu écraseras le lionceau et le dragon.
14 “Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
«Puisqu'il s'est attaché à moi, je le délivrerai; Je le mettrai en sûreté, puisqu'il connaît mon nom.
15 Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
Il m'invoquera, et je l'exaucerai; Je serai avec lui dans la détresse, Je l'en retirerai et je le glorifierai.
16 Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”
Je le rassasierai de longs jours. Et je lui ferai contempler mon salut.»

< Psalms 91 >