< Psalms 90 >

1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Prière de Moïse, homme de Dieu. Seigneur, tu as été pour nous une retraite D'âge en âge.
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
Avant que les montagnes fussent nées, Et que tu eusses formé la terre et le monde. D'éternité en éternité, tu es Dieu.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Tu réduis l'homme en poussière. Et tu dis: Fils d'Adam, retournez à la terre!
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Car mille ans sont à tes yeux Comme le jour d'hier qui est passé, Comme une veille dans la nuit.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Tu les emportes; ils sont comme un songe. Ils sont comme une herbe qui naît le matin:
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
Elle fleurit le matin, et elle pousse; Le soir, on la coupe et elle sèche.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Nous sommes consumés par ta colère Et anéantis par ton courroux.
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Tu as fait passer devant toi nos iniquités. Et devant la lumière de ta face nos fautes cachées.
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Tous nos jours s'évanouissent devant ton courroux; Nos années disparaissent comme un souffle.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
Les jours de nos années s'élèvent à soixante et dix ans Et, pour les plus robustes, à quatre-vingts; Et ce qui en fait l'orgueil n'est que peine et tourment: Tout cela passe vite, et nous nous envolons!
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Qui connaît la force de ta colère et l'ardeur de ton courroux? Oui ressent la crainte qui t'est due?
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Enseigne-nous à bien compter nos jours. Afin que notre coeur s'ouvre aux leçons de la sagesse!
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Reviens, ô Éternel! Jusques à quand? Aie compassion de tes serviteurs!
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Dès le matin, rassasie-nous de ta bonté, Et nous serons dans l'allégresse et dans la joie Tout le long de nos jours.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Donne-nous autant de jours de joie Que tu nous as donné de jours d'épreuves, Et d'années où nous avons connu le malheur.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Que ta puissance éclate aux yeux de tes serviteurs, Et que ta gloire resplendisse sur leurs enfants!
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
Que la bienveillance de l'Éternel, notre Dieu, repose sur nous! Affermis notre oeuvre entre nos mains. Oui, affermis l'oeuvre de nos mains!

< Psalms 90 >