< Esther 8 >

1 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba Ahaswerusi fún Esteri ayaba ní ilé e Hamani, ọ̀tá àwọn Júù. Mordekai sì wá síwájú ọba, nítorí Esteri ti sọ bí ó ṣe jẹ́ sí ọba.
În acea zi împăratul Ahaşveroş a dat casa lui Haman, duşmanul iudeilor, împărătesei Estera. Şi Mardoheu a venit înaintea împăratului; fiindcă Estera spusese ce îi era ei.
2 Ọba sì bọ́ òrùka dídán an rẹ̀, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ Hamani ó sì fi fún Mordekai, Esteri sì yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí ilé e Hamani.
Şi împăratul şi-a scos inelul, pe care îl luase de la Haman şi l-a dat lui Mardoheu. Şi Estera a pus pe Mardoheu peste casa lui Haman.
3 Esteri sì tún bẹ ọba lórí ìkúnlẹ̀, pẹ̀lú omijé lójú. Ó bẹ̀ ẹ́ kí ó fi òpin sí ètò búburú Hamani ará Agagi, èyí tí ó ti pète fún àwọn Júù.
Şi Estera a vorbit încă o dată înaintea împăratului şi a căzut la picioarele lui şi l-a implorat cu lacrimi să îndepărteze ticăloşia lui Haman agaghitul şi planul lui pe care l-a plănuit împotriva iudeilor.
4 Nígbà náà ni ọba na ọ̀pá aládé wúrà sí Esteri ó sì dìde, ó dúró níwájú rẹ̀.
Atunci împăratul a întins sceptrul de aur spre Estera. Astfel Estera s-a ridicat şi a stat în faţa împăratului.
5 Ó wí pé, “Bí ó bá wu ọba, tí ó bá sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ojúrere tí ó sì rò pé ohun tí ó dára ni láti ṣe, tí ó bá sì ní inú dídùn pẹ̀lú mi, jẹ́ kí a kọ ìwé àṣẹ láti yí ète tí Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, tí ó kọ́ pàṣẹ pé kí a pa àwọn Júù tí wọ́n wà ní gbogbo àgbáyé ìjọba ọba run.
Şi a spus: Dacă face plăcere împăratului şi dacă am găsit favoare înaintea vederii lui şi acest lucru pare drept înaintea împăratului şi eu sunt plăcută în ochii lui, să se scrie pentru a revoca scrisorile plănuite de Haman fiul lui Hamedata agaghitul, pe care le-a scris pentru a nimici pe iudeii care sunt în toate provinciile împăratului:
6 Nítorí báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á tí èmi yóò sì rí kí ibi máa ṣubú lu àwọn ènìyàn mi? Báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á, tí èmi yóò sì máa wo ìparun àwọn ìdílé mi?”
Căci cum aş putea îndura să văd răul care va veni peste poporul meu? Sau cum aş putea îndura să văd nimicirea rudeniei mele?
7 Ọba Ahaswerusi dá Esteri ayaba àti Mordekai ará a Júù náà lóhùn pé, “Nítorí Hamani kọlu àwọn ará a Júù, èmi ti fi ilé e rẹ̀ fún Esteri, wọ́n sì ti ṣo ó kọ́ sórí igi.
Atunci împăratul Ahaşveroş a spus împărătesei Estera şi iudeului Mardoheu. Iată, i-am dat Esterei casa lui Haman, şi pe el l-au spânzurat de spânzurătoare, pentru că şi-a întins mâna împotriva iudeilor.
8 Nísinsin yìí, kọ ìwé àṣẹ mìíràn ní orúkọ ọba bí àwọn Júù ṣe jẹ́ pàtàkì sí ọ, kí o sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì dì í, nítorí kò sí àkọsílẹ̀ tí a bá ti kọ ní orúkọ ọba tí a sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì tí a lè yìí padà.”
Scrieţi de asemenea în favoarea iudeilor, cum vă place, în numele împăratului şi sigilaţi-l cu inelul împăratului: căci înscrisul scris în numele împăratului şi sigilat cu inelul împăratului, nimeni nu îl poate revoca.
9 Lẹ́sẹ̀kan náà àwọn akọ̀wé ọba péjọ ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kẹta, oṣù Sifani. Wọ́n kọ gbogbo àṣẹ Mordekai sí àwọn Júù, àti sí àwọn alákòóso baálẹ̀ àti àwọn ọlọ́lá ìgbèríko mẹ́tàdínláàádóje tí ó lọ láti India títí ó fi dé Kuṣi. Kí a kọ àṣẹ náà ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé àti bí èdè olúkúlùkù àti pẹ̀lú sí àwọn Júù ní ìlànà bí wọ́n ṣe ń kọ̀wé àti èdè e wọn.
Atunci au fost chemaţi scribii împăratului în acel timp în a treia lună, care este luna Sivan, în a douăzeci şi treia zi a ei şi a fost scris conform cu tot ce a poruncit Mardoheu iudeilor şi locotenenţilor şi prefecţilor şi conducătorilor provinciilor care sunt din India până în Etiopia, o sută douăzeci şi şapte de provincii, fiecărei provincii conform scrierii ei şi fiecărui popor după limba lui şi iudeilor conform scrierii lor şi conform limbii lor.
10 Mordekai sì fi àṣẹ ọba Ahaswerusi kọ̀wé, ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀, ó rán an lọ ní kíákíá, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ ayaba, tiwọn yára bí àṣà àwọn tí wọ́n ń gun ẹṣin tí ó yára, ní pàtàkì èyí tí a ń bọ́ fún ọba.
Şi a scris în numele împăratului Ahaşveroş şi l-a sigilat cu inelul împăratului şi a trimis scrisori prin alergători călări, şi călăreţi pe catâri, cămile şi dromaderi tineri:
11 Àṣẹ ọba sì dé ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní gbogbo ìlú láti kó ara wọn jọ kí wọn sì dáàbò bo ara wọn; láti pa, láti run àti láti kọlu ogunkógun orílẹ̀-èdè kórílẹ̀ èdè kankan tàbí ìgbèríko tí ó bá fẹ́ kọlù wọ́n, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn; kí ẹ sì kó gbogbo ohun ìní àwọn ọ̀tá wọn.
Prin care împăratul a dat iudeilor care erau în fiecare cetate să se adune şi să îşi apere viaţa, pentru a nimici, pentru a ucide, şi pentru a face să piară, orice putere a oamenilor şi a provinciei care i-ar asalta, deopotrivă micuţi şi femei şi să prade averile lor,
12 Ọjọ́ tí a yàn fún àwọn Júù ní gbogbo agbègbè ọba Ahaswerusi láti ṣe nǹkan yìí ni ọjọ́ kẹtàlá èyí tí í ṣe oṣù kejìlá, oṣù Addari.
Într-o singură zi în toate provinciile împăratului Ahaşveroş, adică, în a treisprezecea zi a lunii a douăsprezecea, care este luna Adar.
13 Ọkàn ìwé àṣẹ náà ni kí a gbé jáde gẹ́gẹ́ bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ẹ sì jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún gbogbo ènìyàn ìlú nítorí àwọn Júù yóò le è múra ní ọjọ́ náà láti gbẹ̀san fún ara wọn lára àwọn ọ̀tá wọn.
Copia înscrisului poruncii dată fiecărei provincii a fost publicată tuturor popoarelor ca iudeii să fie gata în acea zi să se răzbune pe duşmanii lor.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ ayaba tiwọn yára bí àṣà tí wọ́n ń gun ẹṣin ọba, sáré jáde, wọ́n sáré lọ nípa àṣẹ ọba. A sì tún gbé àṣẹ náà jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa.
Astfel alergătorii care au călărit pe catâri şi cămile au ieşit, fiind grăbiţi şi presaţi de porunca împăratului. Şi hotărârea a fost dată la palatul Susa.
15 Mordekai sì kúrò níwájú ọba, ó wọ aṣọ aláró àti funfun, ó dé adé e wúrà ńlá pẹ̀lú ìgbànú elése àlùkò dáradára, ìlú Susa sì ṣe àjọyọ̀ ńlá.
Şi Mardoheu a ieşit din prezenţa împăratului în veştmânt împărătesc albastru şi alb, şi cu o mare coroană din aur, şi cu o haină de in subţire şi purpură: şi cetatea Susa s-a bucurat şi s-a veselit.
16 Àsìkò ìdùnnú àti ayọ̀, inú dídùn àti ọlá ni ó jẹ́ fún àwọn Júù.
Iudeii au avut strălucire şi veselie şi bucurie şi onoare.
17 Ní gbogbo ìgbèríko àti ní gbogbo ìlú, ní gbogbo ibi tí àṣẹ ọba dé, ni ayọ̀ àti inú dídùn ti wà láàrín àwọn Júù, wọ́n sì ń ṣe àsè àti àjọyọ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tókù sọ ara wọn di Júù nítorí ẹ̀rù àwọn Júù bà wọ́n.
Şi în fiecare provincie şi în fiecare cetate, oriunde au ajuns porunca împăratului şi hotărârea lui, iudeii au avut bucurie şi veselie, ospăţ şi zi bună. Şi mulţi dintre oamenii ţării au devenit iudei; fiindcă teama de iudei a căzut asupra lor.

< Esther 8 >