< Nehemiah 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
Și în ziua a douăzeci și patra a acestei luni copiii lui Israel s-au adunat cu postire și cu pânze de sac și cu țărână asupra lor.
2 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
Și sămânța lui Israel s-a separat de toți străinii și au stat în picioare și au mărturisit păcatele lor și nelegiuirile părinților lor.
3 Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
Și s-au ridicat pe locul lor și au citit în cartea legii DOMNULUI Dumnezeului lor, o a patra parte din zi; și o altă a patra parte au mărturisit și s-au închinat DOMNULUI Dumnezeului lor.
4 Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Atunci au stat în picioare pe trepte, dintre leviți: Ieșua și Bani, Cadmiel, Șebania, Buni, Șerebia, Bani și Chenani și au strigat cu o voce tare către DOMNUL Dumnezeul lor.
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
Atunci leviții Ieșua și Cadmiel, Bani, Hașabnia, Șerebia, Hodiia, Șebania și Petahia au spus: Ridicați-vă în picioare și binecuvântați pe DOMNUL Dumnezeul vostru pentru totdeauna și întotdeauna; și binecuvântat să fie numele tău glorios, care este înălțat mai presus de orice binecuvântare și laudă.
6 Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
Tu, chiar tu, ești singur DOMN; tu ai făcut cerul, cerul cerurilor, cu toată oștirea lor, pământul și toate lucrurile care sunt pe el, mările și tot ce este în ele și tu le păstrezi pe toate; și oștirea cerului ți se închină ție.
7 “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
Tu ești DOMNUL Dumnezeu, care l-ai ales pe Avram și l-ai scos din Urul caldeilor, și i-ai dat numele Avraam;
8 Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
Și i-ai găsit inima credincioasă înaintea ta și ai făcut un legământ cu el că îi vei da țara canaaniților, a hitiților, a amoriților și a pereziților și a iebusiților și a ghirgasiților, că o vei da, spun eu, seminței sale și ți-ai împlinit cuvintele tale, pentru că ești drept;
9 “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
Și ai văzut necazul părinților noștri în Egipt și ai auzit strigătul lor la Marea Roșie;
10 Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
Și ai arătat semne și minuni asupra lui Faraon și asupra tuturor servitorilor săi și asupra întregului popor al țării sale, pentru că ai cunoscut că s-au purtat cu mândrie împotriva lor. Astfel ți-ai făcut un nume, precum este în această zi.
11 Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
Și ai despărțit marea înaintea lor, astfel ei au mers prin mijlocul mării pe uscat; și pe persecutorii lor i-ai aruncat în adâncuri, ca pe o piatră în ape puternice.
12 Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
Mai mult, tu i-ai condus ziua printr-un stâlp de nor; și noaptea printr-un stâlp de foc, pentru a le da lumină pe calea pe care trebuiau să meargă.
13 “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
Tu ai coborât de asemenea pe muntele Sinai și ai vorbit cu ei din cer, și le-ai dat judecăți drepte și legi adevărate, statute bune și porunci;
14 Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
Și le-ai făcut cunoscut sabatul tău sfânt și le-ai poruncit prin mâna lui Moise, servitorul tău, precepte, statute și legi;
15 Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
Și le-ai dat pâine din cer pentru foamea lor și ai scos apă pentru ei din stâncă, pentru setea lor și le-ai promis că vor intra să stăpânească țara pe care ai jurat că le-o vei da.
16 “Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
Dar ei și părinții noștri s-au purtat cu mândrie și și-au înțepenit gâturile și nu au dat ascultare poruncilor tale,
17 Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
Și au refuzat să dea ascultare, nici nu și-au amintit de minunile tale pe care le-ai făcut printre ei; ci și-au înțepenit gâturile și în răzvrătirea lor au rânduit o căpetenie pentru a se întoarce la robia lor; dar tu ești un Dumnezeu gata să ierte, plin de har și milostiv, încet la mânie și de o mare bunătate, și nu i-ai părăsit.
18 nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
Da, când și-au făcut un vițel turnat și au spus: Acesta este Dumnezeul tău care te-a scos din Egipt și au făcut mari batjocuri;
19 “Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
Totuși, tu, în îndurările tale cele multe, nu i-ai părăsit în pustie; stâlpul de nor nu s-a depărtat de ei ziua, pentru a-i conduce pe cale; nici stâlpul de foc noaptea, pentru a le arăta lumină și calea pe care trebuiau să meargă.
20 Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
Le-ai dat de asemenea duhul tău cel bun pentru a-i instrui, și nu le-ai oprit mana ta de la gura lor și le-ai dat apă pentru setea lor.
21 Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
Da, patruzeci de ani i-ai hrănit în pustie; astfel încât nu le-a lipsit nimic; hainele lor nu s-au învechit și picioarele lor nu s-au umflat.
22 “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
Mai mult, le-ai dat împărății și națiuni și i-ai împărțit în ținuturi; astfel, ei au stăpânit țara lui Sihon și țara împăratului Hesbonului și țara lui Og, împăratul Basanului.
23 Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
Pe copiii lor de asemenea i-ai înmulțit ca stelele cerului și i-ai adus în țara pe care ai promis-o părinților lor, că vor intra să o stăpânească.
24 Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
Astfel copiii au intrat și au stăpânit țara și tu ai supus înaintea lor pe locuitorii țării, pe canaaniți, și i-ai dat în mâinile lor, cu împărații lor și pe popoarele țării, ca să le poată face precum au voit.
25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
Și ei au luat cetăți întărite și un pământ gras și au stăpânit case pline de toate bunătățile, fântâni săpate, vii și grădini de măslini și pomi roditori în abundență; astfel ei au mâncat și s-au săturat și s-au îngrășat și s-au desfătat în marea ta bunătate.
26 “Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
Totuși au fost neascultători și s-au răzvrătit împotriva ta și au aruncat legea ta în spatele lor și au ucis pe profeții tăi care au mărturisit împotriva lor pentru a-i întoarce la tine și au făcut mari batjocuri.
27 Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
De aceea i-ai dat în mâna dușmanilor lor, care i-au chinuit; și în timpul tulburării lor, când au strigat către tine, tu i-ai auzit din cer; și conform cu îndurările tale cele multe le-ai dat salvatori, care i-au salvat din mâna dușmanilor lor.
28 “Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
Dar după ce au avut odihnă, din nou au făcut ce este rău înaintea ta; de aceea i-ai lăsat în mâna dușmanilor lor, astfel încât ei au avut stăpânire asupra lor; totuși când s-au întors și au strigat către tine, tu i-ai auzit din cer; și de multe ori i-ai eliberat conform îndurărilor tale;
29 “Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
Și ai mărturisit împotriva lor, ca să îi întorci înapoi la legea ta; totuși s-au purtat cu mândrie și nu au dat ascultare poruncilor tale, ci au păcătuit împotriva judecăților tale (pe care dacă un om le face, va trăi în ele); și și-au retras umărul și și-au înțepenit gâtul și au refuzat să asculte.
30 Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
Totuși mulți ani i-ai răbdat și ai mărturisit împotriva lor prin duhul tău în profeții tăi; totuși ei au refuzat să își plece urechea; de aceea i-ai dat în mâna popoarelor țărilor.
31 Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
Totuși de dragul marilor tale îndurări tu nu i-ai mistuit în întregime, nici nu i-ai părăsit, pentru că tu ești un Dumnezeu plin de har și milostiv.
32 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
De aceea acum, Dumnezeul nostru, marele, puternicul și înfricoșătorul Dumnezeu, care ții legământul și mila, să nu pară mic, înaintea ta, tot acest necaz, care a venit asupra noastră, asupra împăraților noștri, asupra prinților noștri și asupra preoților noștri și asupra profeților noștri și asupra părinților noștri și asupra întregului tău popor, din timpul împăraților Asiriei până în această zi.
33 Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
Dar totuși tu ești just în tot ce a venit asupra noastră, pentru că tu ai lucrat drept, dar noi am lucrat cu stricăciune;
34 Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
Nici împărații noștri, prinții noștri, preoții noștri, nici părinții noștri nu au ținut legea ta, nici nu au dat ascultare poruncilor tale și mărturiilor tale, cu care ai mărturisit împotriva lor.
35 Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
Fiindcă ei nu ți-au servit în împărăția lor și în marea ta bunătate pe care le-ai dat-o și în țara cea întinsă și grasă pe care ai dat-o înaintea lor, nici nu s-au întors de la lucrările lor rele.
36 “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
Iată, noi suntem servitori în această zi; și în țara pe care ai dat-o părinților noștri să mănânce rodul ei și bunătățile ei, iată, noi suntem servitori în ea;
37 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
Și aceasta dă mult venit împăraților pe care i-ai pus peste noi din cauza păcatelor noastre; de asemenea ei au stăpânire peste trupurile noastre și peste vitele noastre după plăcerea lor și noi suntem în mare strâmtorare.
38 “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”
Și pentru toate acestea noi facem un legământ statornic și îl scriem; și prinții noștri, leviții și preoții noștri îl sigilează.

< Nehemiah 9 >