< Job 1 >

1 Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
A fost un om în țara Uț, al cărui nume era Iov; și acel om era desăvârșit și integru și unul care se temea de Dumnezeu și evita răul.
2 A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
Și i s-au născut șapte fii și trei fiice.
3 Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
Averea lui de asemenea era șapte mii de oi și trei mii de cămile și cinci sute de perechi de boi și cinci sute de măgărițe și o gospodărie foarte mare, astfel încât acest om era cel mai mare dintre toți oamenii din est.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
Și fiii lui mergeau și dădeau ospețe în casele lor, fiecare la ziua lui; și trimiteau și chemau pe cele trei surori ale lor să mănânce și să bea cu ei.
5 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
Și se întâmpla, când zilele ospețelor treceau, că Iov trimitea și îi sfințea și se ridica devreme dimineața și aducea ofrande arse conform numărului lor, al tuturor, pentru că Iov spunea: Poate că fiii mei au păcătuit și au blestemat pe Dumnezeu în inimile lor. Astfel făcea Iov continuu.
6 Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
Și a fost o zi când fiii lui Dumnezeu au venit să se prezinte înaintea DOMNULUI; și Satan a venit de asemenea printre ei.
7 Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
Și DOMNUL i-a spus lui Satan: De unde vii? Atunci Satan a răspuns DOMNULUI și a zis: De la cutreierarea pământului și de la umblarea în sus și în jos pe acesta.
8 Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
Și DOMNUL i-a spus lui Satan: Ai luat aminte la servitorul meu Iov, că nu este niciunul asemenea lui pe pământ, un om desăvârșit și integru, unul care se teme de Dumnezeu și evită răul?
9 Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
Atunci Satan a răspuns DOMNULUI și a zis: Se teme Iov de Dumnezeu degeaba?
10 “Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
Nu l-ai îngrădit pe el și casa lui și tot ce are de jur împrejur? Tu ai binecuvântat lucrarea mâinilor sale și averea lui s-a înmulțit în țară.
11 Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
Dar întinde-ți mâna acum și atinge tot ce are el și te va blestema în față.
12 Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
Și DOMNUL i-a spus lui Satan: Iată, tot ce are el este în puterea ta; numai asupra lui să nu îți întinzi mâna. Astfel Satan a plecat din prezența DOMNULUI.
13 Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
Și a fost o zi când fiii săi și fiicele sale mâncau și beau vin în casa fratelui lor mai mare.
14 oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
Și a venit un mesager la Iov și a spus: Boii arau și măgărițele pășteau lângă ei;
15 àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
Și sabeenii au căzut asupra lor și i-au luat; da, au ucis servitorii cu tăișul sabiei; și doar eu singur am scăpat ca să îți aduc vestea.
16 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
În timp ce el încă vorbea, a venit de asemenea un altul și a spus: Focul lui Dumnezeu a căzut din cer și a ars oile și servitorii și i-a mistuit; și doar eu singur am scăpat ca să îți aduc vestea.
17 Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
În timp ce el încă vorbea, a venit de asemenea un altul și a spus: Caldeenii au făcut trei cete și au căzut asupra cămilelor și le-au dus, da, și au ucis servitorii cu tăișul sabiei; și doar eu singur am scăpat ca să îți aduc vestea.
18 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
În timp ce el încă vorbea, a venit de asemenea un altul și a spus: Fiii tăi și fiicele tale mâncau și beau vin în casa fratelui lor mai mare,
19 Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
Și, iată, a venit un vânt mare dinspre pustie și a lovit cele patru colțuri ale casei și ea a căzut peste tineri și ei sunt morți; și doar eu singur am scăpat ca să îți aduc vestea.
20 Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
Atunci Iov s-a ridicat și și-a rupt mantaua și și-a ras capul și a căzut la pământ și s-a închinat,
21 wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
Și a spus: Gol am ieșit din pântecele mamei mele și gol mă voi întoarce acolo: DOMNUL a dat și DOMNUL a luat; binecuvântat fie numele DOMNULUI.
22 Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.
În toate acestea Iov nu a păcătuit, nici nu l-a acuzat pe Dumnezeu prostește.

< Job 1 >