< Psalmów 78 >

1 Pieśń pouczająca. Asafa. Słuchaj, mój ludu, mego prawa, nakłońcie uszu ku słowom moich ust.
Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
2 Otworzę moje usta do przypowieści, opowiem starodawne tajemnice;
Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
3 Cośmy słyszeli i poznali i [co] nam opowiadali nasi ojcowie.
ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
4 Nie zataimy [tego] przed ich synami, opowiemy przyszłemu pokoleniu o chwale PANA, o jego mocy i cudach, które czynił.
Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
5 Ustanowił bowiem świadectwo w Jakubie, nadał prawo w Izraelu i nakazał naszym ojcom, aby je oznajmiali swoim synom;
Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
6 Aby poznało przyszłe pokolenie, synowie, którzy się urodzą; aby powstawszy, przekazywali [je] swoim synom;
nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
7 Żeby pokładali w Bogu nadzieję i nie zapominali o dziełach Boga, lecz strzegli jego przykazań;
Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
8 Żeby nie byli, jak ich ojcowie, pokoleniem opornym i nieposłusznym; pokoleniem, które nie przygotowało swego serca i którego duch nie był wierny Bogu.
Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
9 Synowie Efraima, uzbrojeni i wyposażeni w łuki, w dniu bitwy wycofali się.
Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
10 [Bo] nie strzegli przymierza Boga i nie chcieli postępować według jego prawa.
Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
11 Zapomnieli o jego dziełach i cudach, które im ukazał.
Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
12 Przed ich ojcami czynił cuda w ziemi Egiptu, na polu Soanu.
Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
13 Rozdzielił morze i przeprowadził ich, i sprawił, że wody stanęły jak wał.
Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
14 Prowadził ich w obłoku za dnia, a całą noc w blasku ognia.
Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
15 Rozszczepił skały na pustyni i napoił ich jakby z wielkich głębin.
Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
16 Wydobył strumienie ze skały i sprawił, że wody płynęły jak rzeki.
Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
17 Lecz [oni] jeszcze więcej grzeszyli przeciwko niemu i pobudzili do gniewu Najwyższego na pustyni;
Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
18 I wystawiali Boga na próbę w swych sercach, żądając pokarmu według swego pragnienia.
Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
19 I mówili przeciwko Bogu tymi słowy: Czy Bóg może zastawić stół na tej pustyni?
Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
20 Oto uderzył w skałę i wypłynęły wody, i wezbrały strumienie; czy będzie mógł też dać chleb? Czy przygotuje mięso swemu ludowi?
Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
21 Gdy PAN [to] usłyszał, rozgniewał się i ogień zapłonął przeciw Jakubowi, i gniew wybuchnął przeciw Izraelowi;
Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
22 Bo nie uwierzyli Bogu i nie zaufali jego zbawieniu;
nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
23 Choć rozkazał chmurom w górze i bramy nieba otworzył.
Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
24 I zesłał im [jak] deszcz mannę do jedzenia, i zboże z nieba im dał.
Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
25 Człowiek jadł chleb anielski; zesłał im pokarm do syta.
Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
26 Wzbudził na niebie wiatr ze wschodu i sprowadził swą mocą wiatr południowy.
Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
27 Zesłał im mięso jak pył i ptactwo skrzydlate jak piasek morski.
Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
28 Spadło ono pośrodku ich obozu, wokół ich namiotów.
Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
29 Jedli i w pełni się nasycili; dał im, czego pragnęli.
Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
30 [A gdy] jeszcze nie zaspokoili swego pragnienia, [gdy] jeszcze pokarm był w ich ustach;
Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
31 Spadł na nich gniew Boży i zabił ich tłustych, a znakomitszych z Izraela powalił.
ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
32 Mimo to nadal grzeszyli i nie wierzyli jego cudom;
Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
33 Dlatego sprawił, że ich dni przemijały w marności, a ich lata – w trwodze.
O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
34 Gdy ich zabijał, szukali go; nawracali się i o świcie szukali Boga;
Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
35 Przypominali sobie, że Bóg [jest] ich skałą, że Bóg Najwyższy – ich Odkupicielem;
Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
36 Pochlebiali mu jednak swoimi ustami i okłamywali go swym językiem;
Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
37 A ich serce nie było przed nim szczere i nie byli wierni jego przymierzu.
ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
38 On jednak, będąc miłosiernym, przebaczał ich nieprawości i nie wytracał [ich]; często odwracał swój gniew i nie pobudzał całej swej zapalczywości;
Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
39 Bo pamiętał, że są ciałem; wiatrem, który ulatuje i nie wraca.
Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
40 Jak często pobudzali go do gniewu na pustyni [i] zasmucali go na pustkowiu!
Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
41 Odwracali się i wystawiali Boga na próbę, i stawiali granice Świętemu Izraela.
Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
42 Nie pamiętali jego ręki [ani] dnia, w którym ich wybawił z utrapienia;
Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
43 Gdy czynił swe znaki w Egipcie i swe cuda na polu Soanu;
ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
44 Gdy zamienił w krew ich rzeki i ich strumienie, tak że nie mogli [z nich] pić.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
45 Zesłał na nich rozmaite muchy, aby ich kąsały, i żaby, aby ich niszczyły;
Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
46 I dał robactwu ich plony, a ich pracę szarańczy.
Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
47 Zniszczył gradem ich winorośle, a sykomory szronem.
Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
48 Ich bydło wydał na pastwę gradu, a ich stada [na pastwę] błyskawic.
Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
49 Wylał na nich żar swojego gniewu, zapalczywość, oburzenie i udrękę, zesławszy na nich złych aniołów.
Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
50 Otworzył drogę dla swego gniewu, nie zachował ich duszy od śmierci, a ich życie wydał zarazie;
Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
51 Wytracił wszystko pierworodne w Egipcie, pierwociny [ich] mocy w namiotach Chama;
Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
52 Ale swój lud wyprowadził jak owce i wiódł ich po pustyni jak stado.
Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
53 Prowadził ich bezpiecznie, tak że się nie lękali, a ich wrogów przykryło morze;
Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
54 I przyprowadził ich do swej świętej granicy; do góry, którą nabyła jego prawica.
Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
55 Wypędził przed nimi narody, sznurem wyznaczył im dziedzictwo, żeby pokolenia Izraela mieszkały w swoich namiotach.
Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
56 Oni jednak wystawiali na próbę i pobudzali do gniewu Boga Najwyższego, i nie strzegli jego świadectw.
Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
57 Lecz odwrócili się i postępowali przewrotnie jak ich ojcowie, schodzili z drogi jak łuk zawodny.
Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
58 Pobudzali go bowiem do gniewu przez swe wyżyny i rzeźbionymi posągami wzbudzali jego zazdrość.
Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
59 Gdy Bóg [to] usłyszał, rozgniewał się i wielce wzgardził Izraelem.
Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
60 I opuścił przybytek w Szilo; namiot, [który] rozbił wśród ludzi;
Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
61 I oddał w niewolę swoją moc i swoją chwałę w ręce wroga.
Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
62 Wydał swój lud pod miecz i rozgniewał się na swoje dziedzictwo.
Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
63 Ich młodzieńców pochłonął ogień, a ich dziewic nie wydano za mąż.
Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
64 Ich kapłani padli od miecza, a ich wdowy nie lamentowały.
àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
65 Lecz potem Pan ocknął się jak ze snu, jak mocarz wykrzykujący od wina.
Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
66 I uderzył na tyły swoich wrogów, okrył ich wieczną hańbą.
Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
67 Ale choć wzgardził namiotem Józefa i pokolenia Efraima nie wybrał;
Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
68 Jednak wybrał pokolenie Judy, górę Syjon, którą umiłował.
ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
69 I zbudował swoją świątynię jak wysoki [pałac]; jak ziemię, którą ugruntował na wieki.
Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
70 Wybrał też Dawida, swego sługę; wziął go z owczych zagród;
Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
71 Przywołał go, gdy chodził za karmiącymi [owcami], aby pasł Jakuba, jego lud, i Izraela, jego dziedzictwo.
Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
72 A on ich pasł w prawości swego serca i prowadził ich roztropną ręką.
Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.

< Psalmów 78 >