< Psalmów 77 >

1 Przewodnikowi chóru dla Jedutuna. Psalm Asafa. [Wzniosłem] swój głos do Boga i zawołałem; [wzniosłem] swój głos do Boga i mnie wysłuchał.
Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
2 W dniu mego utrapienia szukałem Pana, moje ręce wyciągałem w nocy nieustannie, moja dusza nie dała się pocieszyć.
Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
3 Gdy wspominałem Boga, byłem strwożony; rozmyślałem, a mój duch był ogarnięty utrapieniem. (Sela)
Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
4 Ty zatrzymujesz otwarte powieki mych oczu, jestem [tak] zaniepokojony, że nie potrafię mówić.
Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
5 Rozpamiętuję dni przeszłe [i] dawne lata.
Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
6 Przypominam sobie mój śpiew; nocą rozmyślam w sercu i mój duch docieka:
mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
7 Czy Pan odrzuci na wieki i już więcej nie okaże łaski?
“Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
8 Czy jego miłosierdzie ustało na zawsze i jego obietnica nigdy się nie spełni?
Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
9 Czy Bóg zapomniał o litości? Czy w gniewie stłumił swoją łaskawość? (Sela)
Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
10 I powiedziałem: To jest moja niemoc; [jednak będę wspominał] lata prawicy Najwyższego.
Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
11 Będę wspominał dzieła PANA, będę wspominał twoje dawne cuda.
Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
12 Będę rozmyślał o wszystkich twoich dziełach i o twoich czynach będę mówił.
Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
13 Boże, święta jest twoja droga; który bóg jest tak wielki, jak [nasz] Bóg?
Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
14 Ty [jesteś] Bogiem, który czyni cuda; dałeś poznać narodom swoją moc.
Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
15 Odkupiłeś [swoim] ramieniem twój lud, synów Jakuba i Józefa. (Sela)
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
16 Widziały cię wody, o Boże, widziały cię wody [i] ulękły się, poruszyły się głębiny.
Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
17 Chmury spłynęły wodą, niebiosa wydały gromy i poleciały twoje strzały.
Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
18 Huk twego grzmotu wśród obłoków, błyskawice oświetliły świat, ziemia poruszyła się i zatrzęsła.
Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
19 Twoja droga [wiodła] przez morze, twoje ścieżki przez wielkie wody i nie było znać twoich śladów.
Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
20 Prowadziłeś swój lud jak stado owiec ręką Mojżesza i Aarona.
Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.

< Psalmów 77 >