< I Kronik 11 >

1 Zebrał się tedy wszystek Izrael do Dawida do Hebronu, mówiąc: Otośmy kość twoja i ciało twoje!
Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
2 Jako i przedtem, gdy jeszcze był Saul królem, też wywodził i wwodził Izraela. Tak Pan, Bóg twój, rzekł tobie: Ty będziesz pasł lud mój Izraelski, a ty będziesz wodzem nad ludem moim Izraelskim.
Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
3 A tak przyszli wszyscy starsi Izraelscy do króla do Hebronu, i uczynił Dawid z nimi przymierze w Hebronie przed Panem, i pomazali Dawida za króla nad Izraelem według słowa Pańskiego, które powiedział przez Samuela.
Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
4 Jechał tedy Dawid ze wszystkim Izraelem do Jeruzalemu, które jest Jebus, gdzie byli Jebuzejczycy obywatelami ziemi.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
5 I rzekli obywatele Jebuzejscy do Dawida: Nie wnijdziesz sam. Ale Dawid wziął zamek Syoński, który jest miastem Dawidowem.
Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
6 Bo był rzekł Dawid: Ktobykolwiek poraził Jebuzejczzyka najpierwej, ten będzie skiążęciem i hetmanem. Przetoż wstąpił najpierw Joab, syn Sarwii, i został hetmanem.
Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
7 I mieszkał Dawid na onym zamku; dla tego nazwano go miastem Dawidowem.
Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
8 I zbudował miasto w około, od Mello aż w okrąg; a Joab pobudował ostatek miasta.
Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
9 A tak Dawid im dalej, tem więcej rozmnażał się, i rosł; albowiem Pan zastępów był z nim.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 A cić są najorzedniejsi rycerze, których miał Dawid, którzy się mężnie starali z nim o królestwo jego ze wszystkim Izraelem, aby go królem uczynili według słowa Pańskiego nad Izraelem.
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
11 A tenci jest poczet rycerzy, których miał Dawid: Jasobam, syn Chachmonowy, przedniejszy między trzydziestoma; ten podniósłszy oszczep swój na trzystu, jednym razem ich zabił.
Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
12 A po nim Elezar, syn Dodonowy, Achochytczyk; ten był jednym między trzema mocarzami.
Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
13 Ten był z Dawidem w Pasdamim, gdzie się zebrali byli Filistynowie ku bitwie; a była ona część pola pełna jęczmienia, a lud był uciekł przed Filistynami.
Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
14 I stanęli w pośród onego pola, i obronili go, a porazili Filistynów: i wybawił Pan lud wybawieniem wielkiem.
Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
15 Ci także trzej ze trzydziestu przedniejszych wstąpili na skałę do Dawida do jaskini Odollam, gdyż wojsko Filistyńskie leżało obozem w dolinie Rafaim;
Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
16 Albowiem Dawid natenczas mieszkał na zamku, a stanowisko Filistyńskie było natenczas w Betlehem.
Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
17 Pragnęł tedy Dawid: Oby mi się kto dał napić wody z studni Betlehemskiej, która jest u bramy!
Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
18 Przetoż przebiwszy się ci trzej przez wojsko Filistyńskie, naczerpali wody z studni Betlehemskiej, która jest u bramy, a wziąwszy przynieśli do Dawida. Lecz jej nie chciał Dawid pić, ale ją wylał na ofiarę Panu.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
19 I rzekł: Nie daj mi tego, Boże mój, abym to uczynić miał! Izali krew tych mężów pić będą, którzy odważyli żywot swój? albowiem z odwagą żywota swego przynieśli ją; i nie chciał jej pić. Toć uczynili trzej oni mocarze.
“Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
20 A Abisaj, brat Joabowy, był przedniejszy z onych trzech; tenże podniósł włócznię swą na trzysta ludu, które pobił, i otrzymał sławę między onymi trzema.
Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
21 Z tych trzech nad innych dwóch był sławniejszy, a był ich książęciem; jednak onych trzech pierwszych nie doszedł.
Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
22 Banajas też, syn Jojady, syn męża dużego, wielkich spraw, z Kabseela, ten zabił dwóch mocarzów Moabskich; ten też zszedłszy zabił lwa w pośród jamy, gdy był śnieg.
Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
23 Ten też zabił męża Egipczanina, męża, którego wzrost był na pięć łokci. A chociaż Egipczanin miał w ręku oszczep jako nawój tkacki, wszkże przyszedł do niego z kijem, i wydarł oszczep z ręki Egipczanina, i zabił go oszczepem jego.
Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
24 To uczynił Banajas, syn Jojady, który także sławnym został między onymi trzema mocarzami.
Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
25 A choć był między onymi trzydziestoma sławnym, wszakże nie doszedł onych trzech. I postanowił go Dawid nad drabantami swymi.
Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
26 A w wojsku co mocniejsi byli: Asael, brat Joabowy, Elkanan, syn Dodonowy z Betlehem;
Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
27 Sammot Harodczyk, Heles Felonitczyk;
Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
28 Hyra, syn Ikkiesowy, Tekuitczyk, Abiezer Anatotczyk;
Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
29 Sybbechaj Husatczyk, Ilaj Ahohytczyk;
Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
30 Maharaj Netofatczyk, Heled, syn Baamy, Netofatczyk;
Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
31 Itaj, syna Rybajego, z Gabaat synów Benjaminowych, Banajas Faratończyk;
Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
32 Hutaj od potoku Gaas; Abiel Arbatczyk;
Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
33 Asmawet Bacharomczyk; Elijachba Salabończyk.
Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
34 Synowie Asema Gisończyka: Jonatan, syn Sagii, Hororczyk;
Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
35 Ahijam, syn Zacharowy, Ararytczyk, Elifal, syn Urowy;
Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
36 Hefer Mecheratczyk, Achijas Felonitczyk;
Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
37 Hesro Karmelczyk, Naaraj, syn Ezbajowy;
Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
38 Joel, brat Natanowy, Michbar, syn Gierego.
Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
39 Selek Ammonitczyk, Nacharaj Berotczyk, który nosił broń Koaba, syna Sarwii;
Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
40 Hyra Itrejczyk, Gareb Itrejczyk;
Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
41 Uryjasz Hetejczyk, Zabad, syn Achalajego.
Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
42 Adyna, syn Sysy, Rubenitczyk, książę Rubenitów, a z nim trzydzieści mężów.
Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
43 Hanan, syn Maachy, i Jozafat Mitnitczyk.
Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
44 Uzyjasz Asteratczyk, Sama i Jehijel, synowie Hotamy Aroerytczyka.
Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
45 Jedinael, syn Symry, i Jocha, brat jego, Tysytczyk.
Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
46 Eliel Machawimczyk, i Jerybaj, i Josawijasz, synowie Elnaamowi, i Itma Moabczyk.
Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
47 Eliel, i Obed, i Jaasyjel z Mezobaj.
Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.

< I Kronik 11 >