< I Kronik 10 >

1 A gdy Filistynowie walczyli z Izraelem, uciekli mężowie Izraelscy przed Filistynami a polegli, będąc porażeni na górze Gielboe.
Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa.
2 I gonili Filistynowie Saula i synów jego; i zabili Filistynowie Jonatana, i Abinadaba, i Melchisuego, synów Saulowych.
Àwọn ará Filistini sí lépa Saulu gidigidi àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n sì pa àwọn ọmọ rẹ̀. Jonatani, Abinadabu àti Malikiṣua.
3 A gdy się zmocniła bitwa przeciw Saulowi, trafili na niego strzelcy, i z łuku zraniony jest od strzelców.
Ogun náà sí gbóná janjan fún Saulu, nígbà tí àwọn tafàtafà sì lé e bá, wọ́n sì ṣá a lọ́gbẹ́.
4 Rzekł tedy Saul do sługi swego, co za nim broń nosił: Dobądź miecza twego, a przebij mię nim, by snać nie przyszli ci nieobrzezańcy, a nie pośmiewali się ze mnie. Ale nie chciał sługa, który nosił broń jego; bo się bardzo bał. Przetoż porwawszy Saul miech, padł nań.
Saulu sì sọ fún ẹni tí ó gbé ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí o sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má wá láti bú mi.” Ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń gbé ìhámọ́ra rẹ̀ ń bẹ̀rù, kò sì le ṣe é, bẹ́ẹ̀ ni Saulu mú idà tirẹ̀ ó sì ṣubú lé e.
5 A widząc sługa, co nosił broń jego, że umarł Saul, padłszy też i sam na miecz umarł.
Nígbà tí agbé-ìhámọ́ra rí pé Saulu ti kú, òhun pẹ̀lú ṣubú lórí idà tirẹ̀, ó sì kú.
6 A tak umarł Saul, i trzej synowie jego, i wszystek dom jego z nim pospołu zginął.
Bẹ́ẹ̀ ni Saulu àti ọmọ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta kú, gbogbo ilé rẹ̀ sì kú ṣọ̀kan, lọ́jọ́ kan náà.
7 Co gdy ujrzeli wszyscy mężowie Izraelscy, którzy mieszkali na dolinie, iż uciekli Izraelczycy, a iż pomarli Saul i synowie jego, opuściwszy miasta swe także uciekli. I przyszli Filistynowie, i mieszkali w nich.
Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ rí wí pé àwọn ọmọ-ogun ti sálọ àti pé Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti kú wọ́n kọ àwọn ìlú wọn sílẹ̀, wọ́n sì sálọ. Àwọn ará Filistini wá, wọ́n sì jókòó nínú wọn.
8 A gdy nazajutrz przyszli Filistynowie brać łupy z pobitych, znaleźli Saula, i synów jego, leżących na górze Gielboe;
Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn ará Filistini wá láti kó òkú, wọ́n rí Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣubú sórí òkè Gilboa.
9 A złupiwszy go wzięli głowę jego, i zbroję jego, i posłali po ziemi Filistyńskiej w około, aby to ogłoszone było przed bałwany ich, i przed ludem.
Wọ́n bọ́ ní aṣọ, wọ́n sì gbé orí rẹ̀ àti ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì rán ìránṣẹ́ lọ káàkiri ilẹ̀ àwọn ará Filistini láti kéde ìròyìn náà láàrín àwọn òrìṣà wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
10 I położyli zbroję jego w domu boga swego, a głowę jego zawiesili w domu Dagonowym.
Wọ́n gbé ìhámọ́ra rẹ̀ sí inú ilé tí wọ́n kọ́ fún òrìṣà wọn, wọ́n sì fi orí rẹ̀ kọ́ sí inú ilé Dagoni.
11 Usłyszawszy tedy wszyscy mężowie Jabes Galaad wszystko, co uczynili Filistynowie Saulowi,
Nígbà tí gbogbo àwọn olùgbé Jabesi—Gileadi gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn ará Filistini ṣe fún Saulu,
12 Powstali wszyscy mężowie mocni, i wzięli ciało Saulowe, i ciało synów jego, a przyniósłszy do Jabes pogrzebli kości ich pod dębem w Jabes, i pościli przez siedm dni.
gbogbo àwọn akọni ọkùnrin wọn lọ láti mú àwọn ará Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n sì kó wọn wá sí Jabesi. Nígbà náà, wọ́n sin egungun wọn sábẹ́ igi óákù ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ fún ọjọ́ méje.
13 A tak umarł Saul dla przestępstwa swego, którem był wystąpił przeciwko Panu, i przeciwko słowu Pańskiemu, któego nie przestrzegał, iż się radził ducha wieszczego, pytając się go;
Saulu kú nítorí kò ṣe òtítọ́ sí Olúwa, kò pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ pẹ̀lú, ó tọ abókùúsọ̀rọ̀ lọ fún ìtọ́sọ́nà.
14 A iż się nie radził Pana, zabił go, a przeniósł królestwo na Dawida, syna Isajego.
Kò sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa pa á, Ó sì yí ìjọba náà padà sọ́dọ̀ Dafidi ọmọ Jese.

< I Kronik 10 >