< II Kronik 36 >

1 Tedy wziął lud ziemi Joachaza, syna Jozyjaszowego, a postanowił go za króla na miejscu ojca jego w Jeruzalemie.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah wọn sì fi jẹ ọba ní Jerusalẹmu ni ipò baba rẹ̀.
2 Dwadzieścia i trzy lata było Joachazowi, gdy począł królować, a trzy miesiące królował w Jeruzalemie.
Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta.
3 Bo go złożył król Egipski w Jeruzalemie, i nałożył winę na onę ziemię sto talentów srebra, i talent złota.
Ọba Ejibiti yọ kúrò lórí ìtẹ́ ní Jerusalẹmu, ó sì bù fún un lórí Juda, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì fàdákà àti tálẹ́ǹtì wúrà kan.
4 I postanowił królem król Egipski Elijakima, brata jego, nad Judą i nad Jeruzalemem, i odmienił imię jego, a nazwał go Joakim; a Joachaza, brata jego, wziąwszy Necho, zawiódł go do Egiptu.
Ọba Ejibiti sì mú Eliakimu, arákùnrin Joahasi, jẹ ọba lórí Juda àti Jerusalẹmu, ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu, ṣùgbọ́n Neko mú Joahasi arákùnrin Eliakimu lọ sí Ejibiti.
5 Dwadzieścia i pięć lat miał Joakim, gdy królować począł, a jedenaście lat królował w Jeruzalemie; i czynił złe przed oczyma Pana Boga swego.
Jehoiakimu sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìlá. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
6 Przeciw któremu wyciągnął Nabuchodonozor, król Babiloński, i związał go dwoma łańcuchami miedzianemi, aby go zawiódł do Babilonu.
Nebukadnessari ọba Babeli sì mú un, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti mú un lọ sí Babeli.
7 Naczynia też domu Pańskiego zniósł Nabuchodonozor do Babilonu, i oddał je do kościoła swego w Babilonie.
Nebukadnessari kó nínú ohun èlò ilé Olúwa lọ si Babeli pẹ̀lú, ó sì fi wọn sí ààfin rẹ̀ ní Babeli.
8 A ostatek spraw Joakimowych, i obrzydłości jego, które czynił, i cokolwiek się znajdowało przy nim, to zapisane w księgach królów Izraelskich i Judzkich. A królował Joachyn, syn jego, miasto niego.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoiakimu, àwọn ohun ìríra tí ó ṣe àti gbogbo ohun tí a rí nípa rẹ̀, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Israẹli àti Juda. Jehoiakini ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 Ośm lat miał Joachyn, gdy królować począł, a trzy miesiące i dziesięć dni królował w Jeruzalemie; i czynił złe przed oczyma Pańskimi;
Jehoiakini sì jẹ́ ẹni ọdún méjìdínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ́ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta àti ọjọ́ mẹ́wàá ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa.
10 Potem po roku posłał król Nabuchodonozor, i kazał go przywieść do Babilonu, i z naczyniem kosztownem domu Pańskiego, a postanowił królem Sedekijasza, brata jego, nad Judą i nad Jeruzalemem.
Ní àkókò òjò, ọba Nebukadnessari ránṣẹ́ sí i ó sì mú un wá sí Babeli, pẹ̀lú ohun èlò dáradára láti ilé Olúwa, ó sì mú arákùnrin Jehoiakini, Sedekiah, jẹ ọba lórí Juda àti Jerusalẹmu.
11 Dwadzieścia i jeden lat miał Sedekijasz, gdy królować począł, a jedenaście lat królował w Jeruzalemie.
Sedekiah jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá.
12 I czynił złe przed oczyma Pana, Boga swego, a nie upokorzył się przed Jeremijaszem prorokiem, który mówił z ust Pańskich.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kò sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Jeremiah wòlíì ẹni tí ó sọ̀rọ̀ Olúwa.
13 Owszem i przeciwko królowi Nabuchodonozorowi powstał, który go był przysięgą zawiązał przez Boga; a zatwardziwszy kark swój uparł się w sercu swojem, aby się nie nawrócił do Pana, Boga Izraelskiego.
Ó sì tún ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Nebukadnessari pẹ̀lú, ẹni tí ó mú kí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra. Ó sì di ọlọ́run líle, ó sì mú ọkàn rẹ̀ le láti má lè yípadà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
14 Wszyscy też przedniejsi kapłani, i lud, wielce rozmnożyli nieprawości według wszystkich obrzydliwości pogańskich; i splugawili dom Pański, który był poświęcił w Jeruzalemie.
Síwájú sí i gbogbo àwọn olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn sì di ẹni tí ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi, pẹ̀lú gbogbo ìríra àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n sì sọ ilé Olúwa di èérí, tí ó ti yà sí mímọ́ ní Jerusalẹmu.
15 A Pan, Bóg ojców ich, posyłał do nich posłów swoich, a posyłał rano wstawając; bo folgował ludowi swemu, i mieszkaniu swemu.
Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn ránṣẹ́ sí wọn láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ síwájú àti síwájú sí i, nítorí tí ó ní ìyọ́nú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ àti sí ibùgbé rẹ̀.
16 Ale oni szydzili z posłów Bożych, i lekce sobie poważyli słów jego, a naśmiewali się z proroków jego, aż przyszła popędliwość Pańska na lud jego, tak, iż żadnego uleczenia nie było.
Ṣùgbọ́n wọ́n ń kùn sí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ọ̀rọ̀ rẹ̀, wọ́n fi àwọn wòlíì rẹ̀ ṣẹ̀sín títí tí ìbínú Olúwa fi ru sórí wọn, sí àwọn ènìyàn rẹ̀ kò sì ṣí àtúnṣe.
17 Bo przywiódł na nich króla Chaldejskiego, który pomordował młodzieńców ich mieczem w domu świątnicy ich, a nie przepuścił ani młodzieńcowi ani pannie, starcowi i zgrzybiałemu; wszystkich podał w ręce jego.
Ó sì mú wá sórí wọn ọba àwọn ará Babeli tí wọ́n bá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn jà pẹ̀lú idà ní ilẹ̀ ibi mímọ́, kò sì ní ìyọ́nú sí àgbà ọkùnrin tàbí ọ̀dọ́mọdébìnrin, wúńdíá, tàbí arúgbó. Ọlọ́run sì fi gbogbo wọn lé Nebukadnessari lọ́wọ́.
18 Nadto wszystkie naczynia domu Bożego, wielkie i małe, i skarby domu Pańskiego, i skarby królewskie i książąt jego, wszystko przeniósł do Babilonu.
Ó sì mú gbogbo ohun èlò láti ilé Ọlọ́run lọ sí Babeli, ńlá àti kékeré àti ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ọba àti ìjòyè rẹ̀.
19 I spalili dom Boży, a zburzyli mury Jeruzalemskie, i wszystkie pałace jego popalili ogniem, i wszystkie jego naczynia kosztowne popsuli.
Wọ́n sì fi iná sun ilé Ọlọ́run, wọ́n sì wó gbogbo ògiri ilé Jerusalẹmu, wọ́n sì jó gbogbo ààfin wọn, wọ́n sì ba gbogbo ohun èlò ibẹ̀ jẹ́.
20 A tych, którzy uszli miecza, przeniósł do Babilonu; i byli niewolnikami jego i synów jego aż do królowania króla Perskiego;
Ó sì kó èyí tí ó kù lọ sí Babeli àwọn tí ó rí ibi sá kúrò lẹ́nu idà wọ́n sì di ìránṣẹ́ fún un àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí tí ìjọba Persia fi gba agbára.
21 Aby się wypełniło słowo Pańskie powiedziane przez usta Jeremijaszowe, ażby odprawiła ziemia sabaty swoje; bo po wszystkie dni spustoszenia swego odpoczywała, aż się wypełniło siedmdziesiąt lat.
Ilẹ̀ náà sì gbádùn ìsinmi rẹ̀, ní gbogbo ìgbà ìdahoro, òun sì ń sinmi títí àádọ́rin ọdún fi pé ní ìmúṣẹ ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ láti ẹnu Jeremiah.
22 Potem roku pierwszego Cyrusa, króla Perskiego, aby się wypełniło słowo Pańskie powiedziane przez usta Jeremijaszowe, wzbudził Pan ducha Cyrusa, króla Perskiego, że kazał obwołać i rozpisać po wszystkiem królestwie swojem, mówiąc:
Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi ọba Persia, kí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a tẹnu Jeremiah sọ bá à le ṣẹ pé, Olúwa run ẹ̀mí Kirusi ọba Persia láti ṣe ìkéde ní gbogbo ìjọba rẹ̀, ó sì kọ ọ́ sínú ìwé pẹ̀lú.
23 Tak mówi Cyrus, król Perski: Wszystkie królestwa ziemi dał mi Pan, Bóg niebieski; i ten mi rozkazał, abym mu zbudował dom w Jeruzalemie, które jest w Judztwie. Kto tedy jest między wami ze wszystkiego ludu jego, który budować chce, z tym niech będzie Pan, Bóg jego, a ten niechaj idzie.
“Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia sọ wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mí ní gbogbo ìjọba ayé yìí, ó sì ti yàn mí láti kọ́ ilé Olúwa fún òun ní Jerusalẹmu ti Juda. Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín le gòkè lọ pẹ̀lú rẹ̀; kí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ kí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.’”

< II Kronik 36 >