< Zephaniah 1 >

1 Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi. Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.
RAB, Yahuda Kralı Amon oğlu Yoşiya zamanında Hizkiya oğlu Amarya oğlu Gedalya oğlu Kuşi oğlu Sefanya'ya şöyle seslendi:
2 “Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò lórí ilẹ̀ náà pátápátá,” ni Olúwa wí.
“Yeryüzünden her şeyi silip süpüreceğim.
3 “Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run kúrò, àti ẹja inú Òkun, àti ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,” ni Olúwa wí.
İnsanları, hayvanları, Gökteki kuşları, Denizdeki balıkları, Kötüleri ve onların günah tuzaklarını silip süpüreceğim. Yok edeceğim insanı yeryüzünden.” İşte böyle diyor RAB.
4 “Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu. Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
“Elimi Yahuda ve Yeruşalim'de yaşayanlara karşı uzatacağım. Baal'dan kalan izleri, Putperest din adamlarıyla kâhinlerin adını, Damlardan gök cisimlerine tapınanları, Hem benim adıma, hem de Molek putu adına ant içip tapınanları, Yolumdan dönenleri, Bana yönelmeyenleri, Kılavuzluğumu istemeyenleri buradan yok edeceğim.”
5 àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé, àwọn tí ń sin ogun ọ̀run, àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra, tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
6 Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa; àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”
7 Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè, nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀. Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀, ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.
Susun Egemen RAB'bin önünde, Çünkü O'nun günü yaklaştı. RAB bir kurban hazırladı, Konuklarını çağırdı.
8 “Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa, Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn ọmọ ọba ọkùnrin, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
“O kurban günü” diyor RAB, “Önderleri, kral oğullarını, Yabancıların geleneklerine uyanları Cezalandıracağım.
9 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà, tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.
İlahların tapınaklarını zorbalık ve hileyle dolduran putperestleri O gün cezalandıracağım.
10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà ibodè ẹja, híhu láti ìhà kejì wá àti ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
Diyorum ki, o gün kentin Balık Kapısı'ndan çığlıklar, İkinci Mahalle'den feryatlar Ve tepelerden büyük çatırtılar yükselecek.” İşte böyle diyor RAB.
11 Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní agbègbè ọjà, gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò, gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
“Kentin aşağı mahallesinde oturanlar, feryat edin. Bütün tüccarlarınız yok olacak, Gümüş ticareti yapanların hepsi mahvolacak.
12 Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà, èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn, tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn, àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
O gün kandille arayacağım Yeruşalim'in her yanını, İçlerinden, ‘RAB bir şey yapmaz, Ne iyilik eder ne kötülük’ Diyen o rahatına düşkün aymazları cezalandıracağım.
13 Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun, àti ilé wọn yóò sì run. Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n wọn kì yóò gbé nínú ilé náà, wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí wáìnì láti inú rẹ̀.”
Servetleri yağmalanacak. Viraneye dönecek evleri. Yaptıkları evlerde oturamayacak, Diktikleri bağların şarabını içemeyecekler.”
14 “Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀, ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀ kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún àwọn alágbára; ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
RAB'bin büyük günü yaklaştı, Yaklaştı ve çabucak geliyor. Dinleyin, RAB'bin gününde En yiğit asker bile acı acı feryat edecek.
15 ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú, ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú, ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba, ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
Öfke günü o gün! Acı ve sıkıntı, Yıkım ve felaket, Zifiri karanlık bir gün olacak, Bulutlu, koyu karanlık bir gün.
16 ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun sí àwọn ìlú olódi àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.
Surlu kentlere, köşelerdeki yüksek kulelere karşı Savaş borularının çalındığı, Savaş naralarının atıldığı gündür.
17 “Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú, nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa. Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
RAB diyor ki, “İnsanları öyle bir felakete uğratacağım ki, Körler gibi, nereye gittiklerini göremeyecekler. Çünkü bana karşı günah işlediler. Su gibi akacak kanları, Bedenleri yerde çürüyecek.”
18 Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn kì yóò sì le gbà wọ́n là ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.” Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná ìjowú rẹ̀ parun, nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.
RAB'bin öfke gününde, Altınları da gümüşleri de Onları kurtaramayacak. RAB'bin kıskançlık ateşi bütün ülkeyi yakıp yok edecek. RAB ülkede yaşayanların hepsini korkunç bir sona uğratacak.

< Zephaniah 1 >