< Zephaniah 3 >

1 Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Başkaldıran, yozlaşan, acımasız kentin vay haline!
2 Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Söz dinlemedi, ders almadı, RAB'be güvenmedi, Tanrısı'na sığınmadı.
3 Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Yöneticileri kükreyen aslanlar, Önderleri akşam gezen aç kurtlar gibi, Sabaha bir şey bırakmazlar.
4 Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
Peygamberleri sorumsuz ve güvenilmezdir. Kâhinleri kutsal olanı kirletip, Yasayı çarpıtırlar.
5 Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
Ama adil RAB hâlâ o kentte; O haksızlık etmez, Aksatmadan dağıtır adaletini her yeni günün sabahında. Ne var ki, bu yetmiyor haksızları utandırmaya.
6 “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
RAB diyor ki, “Ulusları yok ettim, Kalelerini yıktım, sokaklarını harap ettim. O sokaklardan geçen kimse yok artık. Kentleri viraneye döndü, Eser kalmadı insandan.
7 Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
Halkım benden korkar, Ders alır bundan dedim. O zaman konutlarına dokunmaz, Onları tasarladığım cezaya çarptırmazdım. Ama her türlü kötülüğü yapmaya istekli görünüyorlar.”
8 Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
Bu yüzden, “Bekleyin de görün” diyor RAB, “Ulusları yargılayacağım günü bekleyin. Ulusları toplamaya, Krallıkları bir araya getirmeye, Gazabımı, kızgın öfkemi Üzerlerine dökmeye karar verdim. Çünkü kıskançlığımın ateşi bütün dünyayı yiyip bitirecek.
9 “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
O zaman, hep birlikte beni adımla çağırmaları, Omuz omuza bana hizmet etmeleri için, Halkların dudaklarını pak kılacağım.
10 Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
Dağılmış olan, bana tapan halkım, Kûş ırmaklarının ötesinden Bana sunular getirecek.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
Halkım bana yaptığı bunca kötülük yüzünden utandırılmayacak o gün. Çünkü gururlu, küstah olanları uzaklaştıracağım aralarından. Kutsal dağımda bir daha böbürlenmeyecekler.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
Orada sadece benim adıma sığınan uysal ve alçakgönüllüleri bırakacağım.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
İsrailliler'den geride kalanlar haksızlık etmeyecek, Yalan söylemeyecek, Kimseyi aldatmayacak, Tok karna yatacaklar ve onları korkutan olmayacak.”
14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
Ey Siyon kızı, ezgiler söyle! Ey İsrail, haykır! Yürekten sevin, sevinçle coş, Ey Yeruşalim kızı!
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
RAB senin cezanı kaldırdı, Kovdu düşmanlarını. İsrail'in Kralı RAB seninle. Korkma artık kötülükten.
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
O gün Yeruşalim'e denecek ki, “Korkma, ey Siyon, gevşemesin ellerin.
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
Tanrın RAB, o güçlü Kurtarıcı seninle. Alabildiğine sevinecek senin için, Sevgisiyle seni yenileyecek, ezgilerle coşacak.”
18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
RAB, “Bayramlar için çektiğiniz özlemleri sona erdireceğim” diyor, “Bunlar sizin için ağırlık ve utançtır. Sizi ezenlerin tümünü cezalandıracağım o gün. Düşkünleri kurtaracak, sürgünleri toplayacağım. Utanç içinde kaldıkları bütün ülkelerde Onları yüceltip onurlandıracağım. O zaman sizi toplayıp yurdunuza geri getireceğim. Göreceksiniz, sizi yeniden bayındır kılacak, Dünyanın bütün halkları arasında yüceltip onurlandıracağım.”
19 Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.

< Zephaniah 3 >