< Zechariah 11 >

1 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni, kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run.
Deschide-ţi uşile, Libanule, ca focul să îţi mistuie cedrii.
2 Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú, nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́: hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani, nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.
Urlă, bradule, pentru că cedrul a căzut, pentru că puternicii sunt prădaţi. Urlaţi, stejari ai Basanului, pentru că pădurea cea deasă a fost dată jos.
3 Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn; ògo wọn bàjẹ́; gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún nítorí ògo Jordani bàjẹ́.
Răsună urletul păstorilor, pentru că gloria lor este prădată; răsună răcnetul leilor tineri, pentru că mândria Iordanului este prădată.
4 Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa.
Astfel spune DOMNUL Dumnezeul meu: Paşte turma de măcel;
5 Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn.
Ale căror stăpâni le înjunghie, şi nu se cred vinovaţi; şi cei care le vând, spun: Binecuvântat fie DOMNUL, pentru că sunt bogat; şi păstorii lor nu au milă de ele.
6 Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”
Fiindcă nu voi mai avea milă de locuitorii ţării, spune DOMNUL; ci, iată, voi da pe oameni, pe fiecare în mâna aproapelui său şi în mâna împăratului său; şi ei vor lovi ţara şi nu îi voi elibera din mâna lor.
7 Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà.
Şi voi paşte turma de măcel, pe voi, cele sărace din turmă. Şi mi-am luat două toiege; pe unul l-am numit Frumuseţe şi pe celălalt l-am numit Legături; şi păşteam turma.
8 Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan. Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi.
Într-o lună am nimicit de asemenea trei păstori; şi sufletul meu i-a urât şi sufletul lor de asemenea m-a detestat.
9 Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”
Atunci am spus: Nu vă voi mai paşte; cea care moare, să moară; şi cea care trebuie stârpită, să fie stârpită; şi restul să mănânce, fiecare, carnea celeilalte.
10 Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá.
Şi mi-am luat toiagul, Frumuseţe, şi l-am tăiat în două, ca să rup legământul meu pe care l-am făcut cu toate popoarele.
11 Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.
Şi a fost rupt în acea zi: şi astfel, cei săraci ai turmei, care m-au aşteptat, au cunoscut că acesta era cuvântul DOMNULUI.
12 Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.
Şi le-am spus: Dacă credeţi că este bine, daţi-mi plata mea; iar dacă nu, lăsaţi-o. Astfel ei mi-au cântărit ca preţ, treizeci de arginţi.
13 Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.
Şi DOMNUL mi-a spus: Aruncă-l olarului: un preţ frumos cu care am fost preţuit de ei. Şi am luat cei treizeci de arginţi şi i-am aruncat olarului, în casa DOMNULUI.
14 Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.
Atunci am tăiat în două celălalt toiag al meu, Legături, ca să rup înfrăţirea dintre Iuda şi Israel.
15 Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀.
Şi DOMNUL mi-a spus: Ia-ţi şi uneltele unui păstor nebun.
16 Nítorí Èmi o gbé Olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
Pentru că, iată, voi ridica un păstor în ţară care nu va cerceta pe cele care sunt stârpite, nici nu va căuta pe cea tânără, nici nu va vindeca pe cea rănită, nici nu va paşte pe cea care stă pe loc; ci carnea celor îngrăşate va mânca şi le va rupe copitele în bucăţi.
17 “Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà, tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀! Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀: apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá, ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”
Vai de păstorul idolatru, ce părăseşte turma! Sabia va fi pe braţul lui şi pe ochiul lui drept; braţul lui va fi uscat deplin şi ochiul lui drept va fi deplin întunecat.

< Zechariah 11 >