< Zechariah 10 >

1 Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
Cereţi de la DOMNUL ploaie la timpul ploii târzii; astfel DOMNUL va face nori strălucitori şi le va da averse de ploaie, la fiecare om verdeaţă în câmp.
2 Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
Pentru că idolii au vorbit deşertăciune şi ghicitorii au văzut o minciună şi au istorisit vise false; ei mângâie în deşert; de aceea ei au mers pe calea lor ca o turmă, s-au tulburat pentru că nu era păstor.
3 “Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
Mânia mea s-a aprins împotriva păstorilor şi am pedepsit ţapii, pentru că DOMNUL oştirilor a cercetat turma sa, casa lui Iuda, şi i-a făcut ca pe calul său ales în luptă.
4 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
Din el a ieşit colţul, din el cuiul, din el arcul de bătălie, din el fiecare opresor laolaltă.
5 Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
Şi ei vor fi ca războinici care calcă pe duşmanii lor, în noroiul străzilor, în bătălie; şi vor lupta, pentru că DOMNUL este cu ei şi cei călare pe cai vor fi încurcaţi.
6 “Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
Şi voi întări casa lui Iuda şi voi salva casa lui Iosif, şi îi voi aduce pentru a-i pune înapoi, pentru că am milă de ei; şi vor fi ca şi cum nu i-aş fi lepădat, pentru că eu sunt DOMNUL Dumnezeul lor şi îi voi auzi.
7 Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
Şi cei din Efraim vor fi ca un războinic; şi inima lor se va bucura ca de vin; da, copiii lor vor vedea aceasta şi se vor veseli; inima lor se va bucura în DOMNUL.
8 Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
Eu voi şuiera după ei şi îi voi aduna, pentru că i-am răscumpărat; şi se vor înmulţi precum se înmulţeau înainte.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
Şi îi voi semăna printre popoare, iar ei îşi vor aminti de mine în ţări îndepărtate; şi vor trăi, ei şi copiii lor, şi se vor întoarce din nou.
10 Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
De asemenea îi voi aduce din nou din ţara Egiptului şi îi voi aduna din Asiria şi îi voi duce în ţara Galaadului şi în Liban şi loc nu va fi găsit pentru ei.
11 Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
Şi el va trece prin mare cu necaz şi va lovi valurile în mare şi toate adâncurile râului se vor usca; şi mândria Asiriei va fi coborâtă şi sceptrul Egiptului se va îndepărta.
12 Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Şi îi voi întări în DOMNUL; şi ei vor umbla în sus şi în jos în numele său, spune DOMNUL.

< Zechariah 10 >