< Ruth 1 >

1 Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
Şi s-a întâmplat, în zilele când judecătorii conduceau, că era o foamete în ţară. Şi un anumit bărbat din Betleem-Iuda a mers să locuiască temporar în ţara Moabului, el şi soţia lui şi cei doi fii ai lui.
2 Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
Şi numele bărbatului era Elimelec şi numele soţiei lui, Naomi, şi numele celor doi fii ai lui erau Mahlon şi Chilion, efratiţi din Betleem-Iuda. Şi au venit în ţara Moabului şi au rămas acolo.
3 Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
Şi Elimelec, soţul lui Naomi, a murit; şi ea a fost lăsată cu cei doi fii ai ei.
4 Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
Şi ei şi-au luat soţii dintre femeile Moabului, numele uneia era Orpa şi numele celeilalte, Rut; şi au locuit acolo cam zece ani.
5 Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
Şi Mahlon şi Chilion au murit de asemenea amândoi; şi femeia a fost lăsată fără cei doi fii ai ei şi fără soţul ei.
6 Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
Atunci s-a ridicat cu nurorile ei să se întoarcă din ţara Moabului; fiindcă auzise în ţara Moabului cum DOMNUL cercetase pe poporul său, dându-le pâine.
7 Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
De aceea a ieşit din locul unde era şi cele două nurori ale ei au ieşit împreună cu ea; şi au pornit la drum să se întoarcă în ţara lui Iuda.
8 Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
Şi Naomi le-a spus celor două nurori ale ei: Duceţi-vă, întoarceţi-vă fiecare la casa mamei sale; DOMNUL să se poarte bine cu voi, precum şi voi v-aţi purtat cu cei morţi şi cu mine.
9 Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
DOMNUL să vă dea să găsiţi odihnă, fiecare în casa soţului ei. Apoi le-a sărutat; iar ele şi-au ridicat vocea şi au plâns.
10 Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
Şi i-au spus: Ne vom întoarce negreşit cu tine la poporul tău.
11 Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
Iar Naomi a spus: Întoarceţi-vă, fiicele mele, de ce să mergeţi cu mine? Mai sunt încă fii în pântecele meu ca să fie soţii voştri?
12 Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
Întoarceţi-vă, fiicele mele, duceţi-vă; fiindcă sunt prea bătrână să am soţ. Dacă aş spune: Am speranţă, dacă aş avea un soţ chiar în această noapte şi de asemenea aş naşte fii,
13 ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
Aţi aştepta pentru ei până când ar fi mari? Aţi sta pentru ei fără a avea soţi? Nu, fiicele mele; fiindcă sunt mâhnită mult pentru voi, pentru că mâna DOMNULUI a ieșit împotriva mea.
14 Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
Şi ele şi-au ridicat vocea şi au plâns din nou; şi Orpa a sărutat pe soacra ei, dar Rut s-a lipit de ea.
15 Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
Şi a spus: Iată, cumnata ta s-a întors la poporul ei şi la dumnezeii ei; întoarce-te şi tu după cumnata ta.
16 Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
Şi Rut a spus: Nu mă ruga să te părăsesc, sau să mă întorc şi să nu te urmez, fiindcă oriunde mergi, voi merge şi eu; şi unde găzduieşti tu, voi găzdui şi eu; poporul tău va fi poporul meu, şi Dumnezeul tău, Dumnezeul meu.
17 Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
Unde mori tu, voi muri şi eu, şi acolo voi fi îngropată; astfel să îmi facă DOMNUL, şi de asemenea mai mult, dacă altceva decât moartea mă va despărţi de tine.
18 Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
Când a văzut că era hotărâtă să meargă cu ea, atunci a încetat să îi mai vorbească.
19 Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
Astfel ele două au mers până au ajuns la Betleem. Şi s-a întâmplat, când au ajuns la Betleem, că toată cetatea s-a pus în mişcare în jurul lor; iar ei au spus: Este aceasta Naomi?
20 Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
Şi ea le-a spus: Nu mă numiţi Naomi, numiţi-mă Mara, fiindcă Cel Atotputernic s-a purtat foarte amar cu mine.
21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
Am plecat plină, şi DOMNUL m-a adus înapoi acasă deşartă; de ce mă numiţi Naomi, văzând că DOMNUL a mărturisit împotriva mea, şi Cel Atotputernic m-a chinuit?
22 Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
Astfel s-a întors Naomi, şi cu ea Rut moabita, nora ei, care s-a întors din ţara Moabului; şi au ajuns la Betleem la începutul secerişului orzului.

< Ruth 1 >