< 1 Samuel 1 >

1 Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
Și era un anumit bărbat din Ramataim-Țofim, din muntele Efraim, și numele lui era Elcana, fiul lui Ieroham, fiul lui Elihu, fiul lui Tohu, fiul lui Țuf, un efraimit;
2 Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
Și el avea două soții; numele uneia era Ana și numele celeilalte Penina; și Penina avea copii, dar Ana nu avea copii.
3 Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
Și acest bărbat se urca în fiecare an, din cetatea sa, pentru a se închina și a sacrifica DOMNULUI oștirilor la Șilo. Și acolo erau cei doi fii ai lui Eli, Hofni și Fineas, preoții DOMNULUI.
4 Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
Și când era timpul ca Elcana să aducă ofrandă, el dădea porții soției sale Penina și la toți fiii și fiicele ei.
5 Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
Dar lui Ana îi dădea o parte aleasă, pentru că o iubea pe Ana; dar DOMNUL îi închisese pântecele.
6 Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
Și potrivnica ei de asemenea o provoca foarte mult, pentru a o chinui, deoarece DOMNUL îi închisese pântecele.
7 Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
Și așa făcea Elcana an de an; când se urca ea la casa DOMNULUI, cealaltă o provoca astfel; de aceea ea plângea și nu mânca.
8 Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
Atunci Elcana, soțul ei, i-a spus: Ana, de ce plângi? Și de ce nu mănânci? Și de ce este inima ta mâhnită? Nu sunt eu mai bun pentru tine decât zece fii?
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
Și Ana s-a ridicat după ce au mâncat și au băut la Șilo. Și preotul Eli ședea pe un scaun lângă unul dintre ușorii templului DOMNULUI.
10 Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Și ea avea sufletul amărât și s-a rugat DOMNULUI și a plâns mult.
11 Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
Și a făcut o promisiune și a spus: DOAMNE al oștirilor, dacă voiești să vezi necazul roabei tale și să îți amintești de mine și să nu uiți pe roaba ta, ci voiești să dai roabei tale un copil de parte bărbătească, atunci îl voi da DOMNULUI în toate zilele vieții lui și briciul nu va trece pe capul lui.
12 Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
Și s-a întâmplat, pe când ea continua să se roage înaintea DOMNULUI, că Eli a luat seama la gura ei.
13 Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
Și Ana vorbea în inima ei; numai buzele i se mișcau, dar vocea nu i se auzea; de aceea Eli gândea că era beată.
14 Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
Și Eli i-a spus: Până când vei fi beată? Depărtează vinul tău de la tine.
15 Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
Și Ana a răspuns și a zis: Nu, domnul meu, eu sunt o femeie cu duhul întristat; nu am băut nici vin, nici băutură tare, ci mi-am turnat sufletul înaintea DOMNULUI.
16 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
Nu lua pe roaba ta drept o fiică a lui Belial, pentru că din marea mea plângere și întristare am vorbit până acum.
17 Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
Atunci Eli a răspuns și a zis: Du-te în pace; și Dumnezeul lui Israel să îți împlinească rugămintea care ai cerut-o de la el.
18 Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
Și ea a spus: Să găsească roaba ta favoare în ochii tăi. Astfel femeia a mers pe calea ei și a mâncat și fața ei nu mai era tristă.
19 Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
Și ei s-au sculat devreme dimineața și s-au închinat înaintea DOMNULUI și s-au întors și au venit la casa lor în Rama. Și Elcana a cunoscut-o pe Ana, soția sa; și DOMNUL și-a amintit de ea.
20 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
Și s-a întâmplat, când s-a împlinit timpul, după ce Ana rămăsese însărcinată, că a născut un fiu și i-a pus numele Samuel, spunând: Pentru că l-am cerut de la DOMNUL.
21 Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
Și bărbatul Elcana și toată casa lui, s-au urcat să sacrifice DOMNULUI sacrificiul anual și să își împlinească promisiunea.
22 Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
Dar Ana nu s-a urcat, pentru că a spus soțului ei: Nu voi urca până când pruncul va fi înțărcat și atunci îl voi duce să se înfățișeze înaintea DOMNULUI și să stea acolo pentru totdeauna.
23 Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
Și Elcana, soțul ei, i-a spus: Fă cum ți se pare bine; rămâi până îl vei fi înțărcat; numai să își întemeieze DOMNUL cuvântul său. Astfel femeia a rămas și și-a alăptat fiul până l-a înțărcat.
24 Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
Și după ce l-a înțărcat, l-a urcat cu ea, luând trei tauri și o efă de făină și un burduf cu vin și l-a adus în casa DOMNULUI, la Șilo; și copilul era mic.
25 Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
Și au înjunghiat un taur; și au adus pe băiat la Eli.
26 Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
Și ea a spus: O, domnul meu, precum sufletul tău trăiește, domnul meu, eu sunt femeia care a stat lângă tine aici, rugându-se DOMNULUI.
27 Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
Pentru acest copil m-am rugat; și DOMNUL mi-a ascultat rugămintea pe care am cerut-o de la el.
28 Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.
De aceea l-am împrumutat și eu DOMNULUI; atât cât va trăi, el va fi împrumutat DOMNULUI. Și el s-a închinat DOMNULUI acolo.

< 1 Samuel 1 >