< Romans 9 >
1 Òtítọ́ ni èmi ń sọ nínú Kristi, èmi kò ṣèké, ọkàn mi sì ń jẹ́ mi ní ẹ̀rí nínú Ẹ̀mí Mímọ́.
Eu spun adevărul în Hristos. Nu mint, conștiința mea mărturisește cu mine în Duhul Sfânt
2 Pé mo ní ìbìnújẹ́ púpọ̀, àti ìkáàánú ìgbà gbogbo ni ọkàn mi.
că am o mare întristare și o durere neîncetată în inima mea.
3 Nítorí mo fẹ́rẹ lè gbàdúrà pé kí èmi tìkára mi kúrò lọ́dọ̀ Kristi nítorí àwọn ará mi, àwọn ìbátan mi nípa ti ara.
Căci aș putea să doresc să fiu eu însumi blestemat de Cristos, din cauza fraților mei, rudele mele după trup
4 Àwọn ẹni tí i ṣe Israẹli; tí àwọn ẹni tí ìsọdọmọ í ṣe, àti ògo, àti májẹ̀mú, àti ìfúnilófin, àti ìsìn Ọlọ́run, àti àwọn ìlérí.
care sunt israeliți; a căror adopție, glorie, legăminte, dăruire a legii, slujire și promisiuni
5 Tí ẹni tí àwọn Baba í ṣe, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹni tí Kristi ti wá nípa ti ara, ẹni tí ó borí ohun gbogbo, Ọlọ́run olùbùkún láéláé. Àmín. (aiōn )
din care sunt părinții și din care provine Cristos în ceea ce privește trupul, care este peste toate, Dumnezeu, binecuvântat în veci. Amin. (aiōn )
6 Ṣùgbọ́n kì í ṣe pé nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán. Kì í sá í ṣe gbogbo àwọn tí ó ti inú Israẹli wá, àwọn ni Israẹli.
Dar nu este ca și cum Cuvântul lui Dumnezeu ar fi fost zădărnicit. Căci nu toți cei din Israel sunt din Israel.
7 Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé, nítorí wọ́n jẹ́ irú-ọmọ Abrahamu, gbogbo wọn ni ọmọ. Ní ọ̀nà mìíràn, “Nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.”
și nici, pentru că sunt urmașii lui Avraam, nu sunt toți copii. Ci, “urmașii voștri vor fi socotiți ca de la Isaac”.
8 Èyí nì ni pé, kì í ṣe àwọn ọmọ nípa ti ara ni ọmọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ìlérí ni a kà ní irú-ọmọ.
Adică, nu copiii cărnii sunt copiii lui Dumnezeu, ci copiii promisiunii sunt socotiți moștenitori.
9 Nítorí ọ̀rọ̀ ìlérí ni èyí: “Ní ìwòyí àmọ́dún ni èmi yóò wá, Sara yóò sì ní ọmọ ọkùnrin.”
Căci acesta este un cuvânt al promisiunii: “La timpul hotărât voi veni și Sara va avea un fiu”.
10 Kì í sì í ṣe kìkì èyí, ṣùgbọ́n nígbà tí Rebeka pẹ̀lú lóyún fún ẹnìkan, fún Isaaki baba wa.
Și nu numai atât, ci și Rebeca a conceput un fiu, pe tatăl nostru Isaac.
11 Nítorí nígbà tí kò tí ì bí àwọn ọmọ náà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tí ì ṣe rere tàbí búburú—kí ìpinnu Ọlọ́run nípa ti ìyànfẹ́ kí ó lè dúró,
Căci, nefiind încă născută, și neavând nimic bun sau rău, pentru ca scopul lui Dumnezeu, potrivit alegerii, să rămână în picioare, nu din fapte, ci de la Cel care cheamă,
12 kì í ṣe nípa ti iṣẹ́, bí kò ṣe ti ẹni tí ń peni—a ti sọ fún un pé, “Ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
i s-a spus: “Cel mai mare va sluji celui mai mic”.
13 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Jakọbu ni mo fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra.”
Așa cum este scris: “Pe Iacov l-am iubit, dar pe Esau l-am urât”.
14 Ǹjẹ́ àwa yóò ha ti wí? Àìṣòdodo ha wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run bí? Kí a má ri!
Ce vom spune atunci? Există nedreptate la Dumnezeu? Să nu fie niciodată!
15 Nítorí ó wí fún Mose pé, “Èmi ó ṣàánú fún ẹni tí èmi yóò ṣàánú fún, èmi yóò sì ṣe ìyọ́nú fún ẹni tí èmi yóò ṣe ìyọ́nú fún.”
Căci El a zis lui Moise: “Voi avea milă de cine am milă și voi avea milă de cine am milă”.
16 Ǹjẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ti ẹni tí ó fẹ́, kì í sì í ṣe ti ẹni tí ń sáré, bí kò ṣe ti Ọlọ́run tí ń ṣàánú.
Deci, nu este a celui care vrea, nici a celui care aleargă, ci a lui Dumnezeu care are milă.
17 Nítorí ìwé mímọ́ wí fún Farao pé, “Nítorí èyí náà ni mo ṣe gbé ọ dìde, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.”
Căci Scriptura îi spune lui Faraon: “Tocmai pentru aceasta am făcut să te înalț, ca să-mi arăt în tine puterea Mea și ca numele Meu să fie vestit pe tot pământul.”
18 Nítorí náà ni ó ṣe ń ṣàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú ní ọkàn le.
Așadar, El are milă de cine vrea și împietrește pe cine vrea.
19 Ìwọ ó sì wí fún mi pé, “Kín ni ó ha tún bá ni wí sí? Nítorí ta ni ó ń de ìfẹ́ rẹ lọ́nà?”
Atunci îmi veți zice: “De ce mai găsește el greșeală? Căci cine se împotrivește voinței lui?”
20 Bẹ́ẹ̀ kọ́, ìwọ ènìyàn, tà ni ìwọ tí ń dá Ọlọ́run lóhùn? “Ohun tí a mọ, a ha máa wí fún ẹni tí ó mọ ọ́n pé, ‘Èéṣe tí ìwọ fi mọ mi báyìí?’”
Dar, într-adevăr, omule, cine ești tu ca să răspunzi împotriva lui Dumnezeu? Oare lucrul format îl va întreba pe cel care l-a format: “De ce m-ai făcut așa?”
21 Amọ̀kòkò kò ha ni agbára lórí amọ̀, nínú ìṣù kan náà láti ṣe apá kan nínú ohun èlò sí ọlá, àti apá kan nínú ohun èlò sí àìlọ́lá?
Sau nu are olarul un drept asupra lutului, din aceeași bucată să facă dintr-o parte un vas pentru cinste și din alta pentru dezonoare?
22 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá fẹ́ fi ìbínú rẹ̀ hàn ń kọ́? Tí ó sì fẹ́ sọ agbára rẹ̀ di mí mọ̀, tí ó sì mú sùúrù púpọ̀ fún àwọn ohun èlò ìbínú tí a ṣe fún ìparun.
Și dacă Dumnezeu, vrând să-și arate mânia și să-și facă cunoscută puterea, a îndurat cu multă răbdare vasele mâniei pregătite pentru distrugere,
23 Àti kí ó lè sọ ọ̀rọ̀ ògo rẹ̀ di mí mọ̀ lára àwọn ohun èlò àánú tí ó ti pèsè ṣáájú fún ògo.
și ca să facă cunoscută bogăția gloriei sale pe vasele milei, pe care le-a pregătit mai dinainte pentru glorie—
24 Àní àwa, tí ó ti pè, kì í ṣe nínú àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nínú àwọn Kèfèrí pẹ̀lú?
pe noi, pe care ne-a chemat și pe noi, nu numai dintre iudei, ci și dintre neamuri?
25 Bí ó ti wí pẹ̀lú ní Hosea pé, “Èmi ó pe àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mi, ní ‘ènìyàn mi’, àti ẹni tí kí í ṣe àyànfẹ́ ní ‘àyànfẹ́.’”
După cum spune și în Osea, “Îi voi numi “poporul meu”, pe cei care nu erau poporul meu; și “iubitul” ei, care nu era iubit.”
26 Yóò sì ṣe, “Ní ibi ti a gbé ti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó gbé pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’”
În locul în care li s-a spus: “Voi nu sunteți poporul Meu”. acolo vor fi numiți “copiii Dumnezeului celui viu”.”
27 Isaiah sì kígbe nítorí Israẹli pé: “Bí iye àwọn ọmọ Israẹli bá rí bí iyanrìn Òkun, apá kan ni ó gbàlà.
Isaia strigă cu privire la Israel, “Dacă numărul copiilor lui Israel este ca nisipul mării, rămășița este cea care va fi salvată;
28 Nítorí Olúwa yóò mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ lórí ilẹ̀ ayé, yóò parí rẹ̀, yóò sì ké e kúrò ní òdodo.”
Căci El va isprăvi lucrarea și o va curma cu dreptate, pentru că Domnul va face o lucrare scurtă pe pământ.”
29 Àti bí Isaiah ti wí tẹ́lẹ̀: “Bí kò ṣe bí Olúwa àwọn Ọmọ-ogun ti fi irú-ọmọ sílẹ̀ fún wa, àwa ìbá ti dàbí Sodomu, a bá sì ti sọ wá dàbí Gomorra.”
După cum a spus Isaia mai înainte, “Dacă Domnul oștirilor nu ne-ar fi lăsat o sămânță, am fi devenit ca Sodoma, și ar fi fost făcut ca Gomora.”
30 Ǹjẹ́ kí ni àwa ó ha wí? Pé àwọn Kèfèrí, tí kò lépa òdodo, ọwọ́ wọn tẹ òdodo, ṣùgbọ́n òdodo tí ó ti inú ìgbàlà wá ni.
Ce vom spune atunci? Că neamurile, care nu urmăreau neprihănirea, au ajuns la neprihănire, la neprihănirea care vine din credință;
31 Ṣùgbọ́n Israẹli ti ń lépa òfin òdodo, ọwọ́ wọn kò tẹ òfin òdodo.
dar Israel, care urmărea o lege a neprihănirii, nu a ajuns la legea neprihănirii.
32 Nítorí kí ni? Nítorí wọn kò wá a nípa ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni pé nípa iṣẹ́ òfin. Nítorí wọn kọsẹ̀ lára òkúta ìkọ̀sẹ̀ ni.
De ce? Pentru că nu au căutat-o prin credință, ci ca și cum ar fi fost prin faptele legii. S-au împiedicat de piatra de poticnire,
33 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Kíyèsi, mo gbé òkúta ìkọ̀sẹ̀ kalẹ̀ ní Sioni àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú, ẹnikẹ́ni ti ó bá sì gbà a gbọ́, ojú kì yóò tì í.”
așa cum este scris, “Iată, pun în Sion o piatră de poticnire și o stâncă de jignire; și nimeni care crede în El nu va fi dezamăgit.”