< Acts 1 >

1 Nínú ìwé mi ìṣáájú, Teofilu, ni mo ti kọ ní ti ohun gbogbo tí Jesu bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àti kọ́
Prima carte pe care am scris-o, Teofilule, se referă la tot ce a început Isus să facă și să învețe,
2 títí ó fi di ọjọ́ tí a gbà á lọ sókè ọ̀run, lẹ́yìn tí ó ti ti ipa Ẹ̀mí Mímọ́ pàṣẹ fún àwọn aposteli tí ó yàn.
până în ziua în care a fost înălțat, după ce a dat poruncă prin Duhul Sfânt apostolilor pe care îi alesese.
3 Lẹ́yìn ìjìyà rẹ̀, ó fi ara rẹ̀ hàn fún wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀rí tí ó dájú pé òun wà láààyè. Ó fi ara hàn wọ́n fún ogójì ọjọ́, ó sì sọ̀rọ̀ nípa ìjọba Ọlọ́run.
Acestora li s-a arătat viu și după ce a suferit, prin multe dovezi, arătându-li-se pe parcursul a patruzeci de zile și vorbindu-le despre Împărăția lui Dumnezeu.
4 Ní àkókò kan bí ó sì ti ń jẹun pẹ̀lú wọn, ó pàṣẹ yìí fún wọn, “Ẹ má ṣe kúrò ní Jerusalẹmu, ṣùgbọ́n ẹ dúró de ìlérí tí Baba mi ṣe ìlérí, èyí tí ẹ̀yin tí gbọ́ lẹ́nu mi.
Fiind adunat împreună cu ei, le-a poruncit: “Nu plecați din Ierusalim, ci așteptați promisiunea Tatălui, pe care ați auzit-o de la mine.
5 Nítorí Johanu fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ díẹ̀ sí i, a o fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.”
Căci Ioan a botezat într-adevăr în apă, dar voi veți fi botezați în Duhul Sfânt nu peste multe zile”.
6 Nítorí náà, nígbà tí wọ́n sì péjọpọ̀, wọn bi í léèrè pé, “Olúwa, láti ìgbà yí lọ ìwọ yóò ha mú ìjọba padà fún Israẹli bí?”
Când s-au adunat, L-au întrebat: “Doamne, acum dai înapoi împărăția lui Israel?”
7 Ó sì wí fún wọn pé, “Kì í ṣe tiyín ni láti mọ àkókò tàbí ìgbà tí Baba ti yàn nípa àṣẹ òun tìkára rẹ̀.
El le-a zis: “Nu este treaba voastră să cunoașteți vremurile și timpurile pe care Tatăl le-a pus în autoritatea Sa.
8 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò gba agbára, nígbà tí Ẹ̀mí Mímọ́ bá bà lé e yín; ẹ̀yin yóò sì máa ṣe ẹlẹ́rìí mi ni Jerusalẹmu, àti ní gbogbo Judea, àti ní Samaria, àti títí dé òpin ilẹ̀ ayé.”
Dar voi veți primi putere când va veni Duhul Sfânt peste voi. Îmi veți fi martori în Ierusalim, în toată Iudeea și Samaria și până la marginile pământului.”
9 Nígbà tí ó sì tí wí nǹkan wọ̀nyí, a gbà á sókè lójú wọn; ìkùùkuu àwọsánmọ̀ sì gbà á kúrò lójú wọn.
După ce a spus aceste lucruri, pe când se uitau ei, a fost ridicat și un nor L-a luat din fața lor.
10 Bí wọ́n sì ti tẹjúmọ́ ojú ọ̀run bí ó ti ń lọ sókè, lójijì, àwọn ọkùnrin méjì tí ó wọ aṣọ funfun dúró létí ọ̀dọ̀ wọn.
În timp ce ei priveau neclintit spre cer, în timp ce El se ducea, iată că lângă ei stăteau doi bărbați îmbrăcați în haine albe,
11 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀yin ara Galili, èéṣe tí ẹ̀yin fi dúró tí ẹ̀ ń wo ojú ọ̀run? Jesu yìí, tí a gbà sókè ọ̀run kúrò lọ́wọ́ yín, yóò padà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí tí ó ń lọ sì ọ̀run.”
care au spus și ei: “Bărbați galileeni, de ce stați cu ochii în cer? Acest Isus, care a fost primit de la voi în cer, se va întoarce în același mod în care L-ați văzut mergând în cer.”
12 Lẹ́yìn náà ni wọ́n padà sí Jerusalẹmu láti orí òkè ti a ń pè ni olifi, tí ó tó ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ ìsinmi kan.
Apoi s-au întors la Ierusalim, de pe muntele numit Muntele Măslinilor, care este lângă Ierusalim, la o zi de drum de Sabat.
13 Nígbà tí wọn sì wọlé, wọn lọ sí iyàrá òkè, níbi tí wọ́n ń gbé. Àwọn tó wà níbẹ̀ ni: Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu; Filipi àti Tomasi; Bartolomeu àti Matiu; Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni Sealoti, àti Judasi arákùnrin Jakọbu.
După ce au ajuns, s-au urcat în camera de sus unde stăteau: Petru, Ioan, Iacov, Iacov, Andrei, Filip, Toma, Bartolomeu, Matei, Iacov, fiul lui Alfeu, Simon Zelota și Iuda, fiul lui Iacov.
14 Gbogbo àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú àwọn obìnrin àti Maria ìyá Jesu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ọkàn kan dúró láti máa gbàdúrà.
Toți aceștia, cu un singur gând, stăruiau cu stăruință în rugăciune și în cereri, împreună cu femeile, cu Maria, mama lui Isus, și cu frații Lui.
15 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni Peteru sí dìde dúró láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn (iye àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ́ ọgọ́fà)
În zilele acelea, Petru s-a ridicat în picioare în mijlocul ucenicilor, care erau în număr de o sută douăzeci, și a zis:
16 ó wí pé, “Ẹ̀yin ará, ìwé mímọ́ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ, èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu Dafidi nípa Judasi, tí ó ṣe atọ́nà fún àwọn tí ó mú Jesu.
“Fraților, trebuia să se împlinească Scriptura aceasta, pe care Duhul Sfânt a spus-o mai înainte, prin gura lui David, despre Iuda, care era călăuza celor ce luaseră pe Isus.
17 Nítorí ọ̀kan nínú wa ni òun ń ṣe tẹ́lẹ̀, òun sì ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí.”
Căci el a fost socotit împreună cu noi și a primit partea lui în această slujbă.
18 (Judasi fi èrè àìṣòótọ́ rẹ̀ ra ilẹ̀ kan; nígbà tí ó sì ṣubú ni ògèdèǹgbé, ó bẹ́ ní agbede-méjì, gbogbo ìfun rẹ̀ sì tú jáde.
Omul acesta a obținut un câmp cu răsplata pentru răutatea lui; și, căzând cu capul în jos, i s-a deschis trupul și i-au țâșnit toate intestinele.
19 Ó si di mí mọ̀ fún gbogbo àwọn ti ń gbé Jerusalẹmu; nítorí náà ni wọ́n fi ń pè ilẹ̀ náà ni Alkedama ní èdè wọn, èyí sì ni, Ilẹ̀ Ẹ̀jẹ̀.)
Toți cei care locuiau în Ierusalim au aflat că în limba lor câmpul acela se numea “Akeldama”, adică “Câmpul de sânge”.
20 Peteru sì wí pé, “Nítorí a ti kọ ọ́ nípa rẹ̀ nínú Ìwé Saamu pé, “‘Jẹ́ ki ibùgbé rẹ̀ di ahoro, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀,’ àti, “‘Ipò rẹ̀ ni kí ẹlòmíràn kí ó gbà.’
Căci este scris în cartea Psalmilor: “Este un câmp de sânge, “Să fie pustiită locuința lui. Nimeni să nu locuiască în ea”. și, “Lasă-l pe altul să își ocupe funcția.
21 Nítorí náà, ó di dandan láti yan ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti ń bá wa rìn ni gbogbo àkókò tí Jesu Olúwa ń wọlé, tí ó sì jáde láàrín wa.
“Așadar, dintre bărbații care ne-au însoțit în tot timpul în care Domnul Isus a intrat și a ieșit dintre noi,
22 Bẹ́ẹ̀ láti ìgbà bamitiisi Johanu títí ó fi di ọjọ́ náà ti a gbe é lọ sókè kúrò lọ́dọ̀ wa. Ó yẹ kí ọ̀kan nínú àwọn wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́rìí àjíǹde rẹ̀ pẹ̀lú wa.”
începând de la botezul lui Ioan și până în ziua în care a fost ridicat de la noi, unul dintre aceștia trebuie să fie martor cu noi al învierii Lui.”
23 Wọn sì yan àwọn méjì, Josẹfu tí a ń pè ní Barsaba (ẹni tí a sọ àpèlé rẹ̀ ni Justu) àti Mattia.
Au propus două: Iosif, zis Barsabas, care se mai numea și Iustus, și Matia.
24 Wọn sì gbàdúrà, wọn sì wí pé, “Olúwa, ìwọ mọ ọkàn gbogbo ènìyàn, fihàn wá nínú àwọn méjì yìí, èwo ni ìwọ yàn
Ei s-au rugat și au zis: “Tu, Doamne, care cunoști inimile tuturor oamenilor, arată pe care dintre acești doi l-ai ales
25 kí ó lè gba ipò nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ aposteli yìí, èyí tí Judasi kúrò nínú rẹ̀, ki òun kí ó lè lọ sí ipò ti ara rẹ̀.”
pentru a lua parte la această slujbă și apostolat, de la care a căzut Iuda, ca să se ducă la locul lui.”
26 Wọ́n sì dìbò fún wọn; ìbò sí mú Mattia; a sì kà á mọ́ àwọn aposteli mọ́kànlá.
Au tras la sorți pentru ei și sorțul a căzut pe Matia; și a fost numărat împreună cu cei unsprezece apostoli.

< Acts 1 >