< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
安息日的诗歌。 称谢耶和华! 歌颂你至高者的名!
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
用十弦的乐器和瑟, 用琴弹幽雅的声音, 早晨传扬你的慈爱; 每夜传扬你的信实。 这本为美事。
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
因你—耶和华借着你的作为叫我高兴, 我要因你手的工作欢呼。
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
耶和华啊,你的工作何其大! 你的心思极其深!
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
畜类人不晓得; 愚顽人也不明白。
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
恶人茂盛如草, 一切作孽之人发旺的时候, 正是他们要灭亡, 直到永远。
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
惟你—耶和华是至高, 直到永远。
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
耶和华啊,你的仇敌都要灭亡; 一切作孽的也要离散。
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
你却高举了我的角,如野牛的角; 我是被新油膏了的。
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
我眼睛看见仇敌遭报; 我耳朵听见那些起来攻击我的恶人受罚。
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
义人要发旺如棕树, 生长如黎巴嫩的香柏树。
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
他们栽于耶和华的殿中, 发旺在我们 神的院里。
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
他们年老的时候仍要结果子, 要满了汁浆而常发青,
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
好显明耶和华是正直的。 他是我的磐石,在他毫无不义。

< Psalms 92 >