< Psalms 91 >
1 Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
Nea ɔte Ɔsorosoroni no hintabea no biara bɛhome wɔ Otumfo no nwini ase.
2 Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
Mese Awurade se, “Ɔyɛ me guankɔbea ne mʼabandennen, me Nyankopɔn a mewɔ no mu ahotoso.”
3 Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
Ampa ara, obegye wo afi firisumfo afiri ne owuyare mu.
4 Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
Ɔde ne ntakra bɛkata wo so; na ne ntaban ase na wubenya guankɔbea; ne nokware bɛyɛ wo nkatabo ne wo kyɛm.
5 Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
Worensuro ɔdasu mu ɔsɛe, anaa bɛmma a etu awia,
6 tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
anaa owuyare a ɛba sum mu, anaa ɔyaredɔm a ɛsɛe ade wɔ owigyinae bere.
7 Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Apem bɛtotɔ wo nkyɛn mu, na mpem du atotɔ wo nifa a, wo de, ɛremmɛn wo.
8 Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
Wʼaniwa nko ara na wode bɛhwɛ na woahu nnebɔneyɛfo asotwe.
9 Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
Sɛ woka se, “Awurade ne me guankɔbea,” na wode Ɔsorosoroni no hɔ yɛ wo tenabea a,
10 Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
ɔhaw biara remmunkam wo so, na ɔsɛe biara remmɛn wo ntamadan.
11 Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
Efisɛ Onyankopɔn bɛsoma nʼabɔfo abɛbɔ wo ho ban na wɔabɛwɛn wo wʼakwan nyinaa mu;
12 wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
wɔde wɔn nsa bɛma wo so, na wo nan ampem ɔbo.
13 Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Wubetiatia gyata ne aprammiri so, wobɛnantew gyataforo ne ɔwɔ so.
14 “Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
Awurade ka se, “Esiane sɛ ɔdɔ me nti, megye no; mɛbɔ ne ho ban, efisɛ ogye me din to mu.
15 Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
Ɔbɛfrɛ me na megye ne so; mɛka ne ho wɔ amanehunu mu, megye no na mahyɛ no anuonyam.
16 Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”
Mɛma nkwa nna a ɛware amee no na makyerɛ no me nkwagye.”