< Psalms 91 >

1 Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
A ki lakik a Legfelsőnek rejtekében, a Mindenhatónak árnyékában honol –
2 Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
azt mondom az Örökkévalóról menedékem és váram, Istenem, a kiben bízom.
3 Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
Mert ő megment téged a madarásznak tőrétől, a veszedelmes dögvésztől.
4 Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
Szárnytollával beföd téged és szárnyai alatt találsz menedéket; paizs és pánczél az ő hűsége.
5 Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
Nem kell félned az éjszaka rettegésétől, a nyíltól, mely nappal repül;
6 tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
a dögvésztől, mely a homályban jár, a pestistől, mely délben pusztít.
7 Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Elhull oldalodról ezer, és tizezer a jobbodról: te hozzád nem közelít.
8 Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
Csak szemeiddel fogod nézni, a gonoszoknak fizetségét látni.
9 Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
Mert te azt mondtad: az Örökkévaló az én menedékem, a Legfelsőt tetted menhelyeddé.
10 Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
Nem esik meg rajtad szerencsétlenség, és csapás nem közeledik sátorodhoz;
11 Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
mert az ő angyalait rendeli melléd, hogy megőrizzenek téged mind az utjaidon.
12 wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
Tenyerükön hordanak téged, hogy kőbe ne üssed lábadat.
13 Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Oroszlán és vipera fölött lépdelsz, letiprasz fiatal oroszlánt és sárkányt.
14 “Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
Mert én rajtam csüng, tehát megszabadítom, megótalmazom, mert ismeri nevemet.
15 Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
Szólít engem és én meghallgatom, vele vagyok szorongatásban, kiragadom és tiszteltté teszem.
16 Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”
Hosszú élettel lakatom jól és látnia engedem segítségemet.

< Psalms 91 >