< Psalms 91 >

1 Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
Mũndũ ũrĩa ũikaraga agitĩirwo nĩ Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno arĩhurũkaga kĩĩruru-inĩ kĩa Mwene-Hinya-Wothe.
2 Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
Ngũkiuga ũhoro wa Jehova atĩrĩ, “Wee nĩwe rĩũrĩro rĩakwa na kĩirigo gĩakwa kĩrĩ hinya, nĩwe Ngai wakwa, ũrĩa ndĩĩhokete.”
3 Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
Ti-itherũ nĩegũgũteithũra gĩkerenge-inĩ kĩa mũtegi, o na kuuma mũrimũ-inĩ ũrĩa mũũru wa kũũraga.
4 Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
Arĩkũhumbagĩra na njoya ciake, na rungu rwa mathagu make nĩho ũrĩĩgitagia; wĩhokeku wake nĩũgatuĩka ngo yaku na kĩĩhitho gĩaku.
5 Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
Ndũrĩĩtigagĩra imakania cia ũtukũ, kana mũguĩ ũrĩa ũthĩrĩrĩkaga mũthenya,
6 tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
o na kana mũrimũ ũrĩa ũceemaga nduma-inĩ, kana mũthiro ũrĩa ũniinanaga mũthenya gatagatĩ.
7 Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Andũ ngiri no magũe mwena waku, nao ngiri ikũmi magũe guoko-inĩ gwaku kwa ũrĩo, no ndũngĩkuhĩrĩrio nĩguo.
8 Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
Wee no kwĩrorera ũkerorera na maitho maku wĩonere iherithia rĩa andũ arĩa aaganu.
9 Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
Ũngĩtua Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno gĩikaro gĩaku, o we Jehova, ũrĩa arĩ we rĩũrĩro rĩakwa,
10 Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
hĩndĩ ĩyo gũtirĩ ũũru ũgaagũkorerera, gũtirĩ mwanangĩko ũgaakuhĩrĩria hema yaku.
11 Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
Nĩgũkorwo nĩagaatha araika ake nĩ ũndũ waku, makũgitagĩre mĩthiĩre-inĩ yaku yothe;
12 wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
nĩmagakuoya na igũrũ na moko mao nĩgeetha ndũkaringwo kũgũrũ nĩ ihiga.
13 Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Nĩũgakinyĩrĩria mũrũũthi, o na nduĩra; ũkarangĩrĩria mũrũũthi ũrĩa mũnene, o na nyoka.
14 “Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Kuona atĩ nĩanyendete, nĩngamũhatũra hatĩka-inĩ; nĩndĩrĩmũgitagĩra, nĩgũkorwo nĩamenyete rĩĩtwa rĩakwa.
15 Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
Arĩngayagĩra, na niĩ ngamwĩtĩka; ndĩrĩkoragwo hamwe nake hĩndĩ ya thĩĩna, ndĩrĩmũteithũraga na ngamũtĩĩithia.
16 Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”
Ngũmũtũũria muoyo matukũ maingĩ nginya aiganie, na ndĩmuonagie ũhonokio wakwa.”

< Psalms 91 >