< Psalms 91 >

1 Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
Khohni kah a huephael ah kho aka sa tah Tlungthang hlip ah rhaehrhong van ni.
2 Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
BOEIPA te, “Ka hlipyingnah neh ka rhalvong,” ka ti eh. Ka Pathen amah dongah ka pangtung eh.
3 Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
Sayuep kah pael neh talnah duektahaw khui lamkah nang te amah loh n'huul ni.
4 Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
A phaemul neh nang n'dah vaengah a phae hmuikah oltak photlinglen neh caempho khuiah na ying ni.
5 Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
Khoyin kah birhihnah khaw, khothaih kah aka thui thaltang te khaw,
6 tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
Khohmuep ah aka pongpa duektahaw khaw, khothun ah aka rhoelrhak sak lucik khaw rhih boeh.
7 Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
Na kaep ah thawngkhat, na bantang ah thawngrha cungku mai cakhaw nang taengla ha thoeih mahpawh.
8 Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
Na mik neh dawk na paelki vaengah halang rhoek kah a phainah te na hmu ni.
9 Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
Namah loh, “BOEIPA tah ka hlipyingnah koinih,” na ti tih Khohni te na khuirhung la na khueh coeng.
10 Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
Yoethae te nang taengla cuhu pawt vetih tlohtat loh na dap taengla ha moe mahpawh.
11 Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
Na longpuei boeih ah nang aka dawn ham a puencawn rhoek te a uen ni.
12 wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
A kut neh nang n'dom uh bitni, lungto dongah na kho na khuek ve.
13 Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Sathuengca neh minta soah na cangdoek vetih, sathuengca neh tuihnam khaw na taelh ni.
14 “Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
Kai taengah a ven uh dongah, anih te ka hlawt van ni. Ka ming a ming dongah, anih te ka hoeptlang ni.
15 Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
Kai n'khue vaengah anih te a taengah ka doo ni. Kai loh citcai khuiah khaw anih te ka pumcum sak vetih, amah ka thangpom ni.
16 Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”
Anih khohnin sen neh ka kodam sak vetih, kamah kah khangnah te ka hmuh sak ni.

< Psalms 91 >