< Psalms 90 >

1 Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
Une prière de Moïse, l'homme de Dieu. Seigneur, tu es notre demeure depuis toutes les générations.
2 Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
Avant que les montagnes ne soient nées, avant que tu aies formé la terre et le monde, même d'éternité en éternité, tu es Dieu.
3 Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
Vous tournez l'homme vers la destruction, en disant, « Revenez, enfants des hommes. »
4 Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
Car mille ans sont à tes yeux comme hier, quand il est passé, comme une veille dans la nuit.
5 Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
Vous les balayez pendant qu'ils dorment. Au matin, ils poussent comme de l'herbe nouvelle.
6 Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
Le matin, il germe et pousse. Le soir, il est flétri et sec.
7 A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
Car nous sommes consumés par ta colère. Nous sommes troublés par ta colère.
8 Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
Tu as mis nos iniquités devant toi, nos péchés secrets dans la lumière de ta présence.
9 Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
Car tous nos jours se sont écoulés dans ta colère. Nous mettons fin à nos années en soupirant.
10 Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
Les jours de nos années sont de soixante-dix, ou même en raison de la force de quatre-vingts ans; mais leur fierté n'est que travail et peine, car il passe vite, et nous nous envolons.
11 Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
Qui connaît la puissance de ta colère, ta colère selon la crainte qui t'est due?
12 Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
Apprenez-nous donc à compter nos jours, afin que nous puissions acquérir un cœur de sagesse.
13 Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
Calme-toi, Yahvé! Combien de temps? Ayez de la compassion pour vos serviteurs!
14 Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
Satisfais-nous dès le matin par ta bonté, afin que nous puissions nous réjouir et être heureux tous les jours.
15 Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
Rends-nous heureux pendant autant de jours que tu nous as affligés, pendant autant d'années que nous avons vu le mal.
16 Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
Que ton travail apparaisse à tes serviteurs, ta gloire à leurs enfants.
17 Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.
Que la faveur du Seigneur notre Dieu soit sur nous. Établissez pour nous le travail de nos mains. Oui, établir le travail de nos mains.

< Psalms 90 >