< Psalms 79 >

1 Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
Un psaume d'Asaph. Dieu, les nations sont entrées dans ton héritage. Ils ont souillé votre temple sacré. Ils ont fait des monceaux de Jérusalem.
2 Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
Ils ont donné les cadavres de tes serviteurs en pâture aux oiseaux du ciel, la chair de tes saints aux animaux de la terre.
3 Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
Ils ont versé leur sang comme de l'eau autour de Jérusalem. Il n'y avait personne pour les enterrer.
4 Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
Nous sommes devenus un opprobre pour nos voisins, une moquerie et une dérision pour ceux qui nous entourent.
5 Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
Combien de temps, Yahvé? Serez-vous toujours en colère? Votre jalousie brûlera-t-elle comme un feu?
6 Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
Répands ta colère sur les nations qui ne te connaissent pas, sur les royaumes qui n'invoquent pas ton nom,
7 nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
car ils ont dévoré Jacob, et a détruit sa patrie.
8 Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
Ne retenez pas contre nous les iniquités de nos ancêtres. Que ta tendre miséricorde nous rejoigne rapidement, car nous en avons désespérément besoin.
9 Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
Aide-nous, Dieu de notre salut, pour la gloire de ton nom. Délivre-nous, et pardonne nos péchés, à cause de ton nom.
10 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
Pourquoi les nations diraient-elles: « Où est leur Dieu? » Que cela soit connu parmi les nations, sous nos yeux, que la vengeance pour le sang de tes serviteurs est en train d'être versée.
11 Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
Laisse les soupirs du prisonnier venir devant toi. Selon la grandeur de ta puissance, préserve ceux qui sont condamnés à mort.
12 San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
Remboursez à nos voisins sept fois dans leur sein l'opprobre dont ils t'ont accablé, Seigneur.
13 Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.
Ainsi nous, ton peuple et les brebis de ton pâturage, vous rendront grâce pour toujours. Nous te louerons pour toujours, pour toutes les générations.

< Psalms 79 >