< Psalms 77 >

1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
Thaburi ya Asafu Ndakaĩire Ngai andeithie; ndakaĩire Ngai nĩguo anjigue.
2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
Rĩrĩa ndaarĩ mĩnyamaro-inĩ, nĩ Mwathani ndarongoririe; ũtukũ ndamwambararĩirie moko itekũnoga, no muoyo wakwa ũkĩrega kũhoorerio.
3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
Wee Ngai, ndakũririkanire ngĩcaaya; ndataranirie maũndũ, naguo roho wakwa ũkĩringĩka.
4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
Wee watũmire njũrwo nĩ toro, ngĩthĩĩnĩka mũno, ngĩremwo nĩ kwaria.
5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
Ndeciiririe ũhoro wa matukũ ma tene, ngĩririkana mĩaka o ĩrĩa yarĩ ya tene;
6 mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
ngĩkĩĩririkania ũrĩa ndainaga ũtukũ, ngoro yakwa ĩgĩtarania maũndũ, naguo roho wakwa ũkĩyũũria atĩrĩ:
7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
“Mwathani egũtũũra atũregete nginya tene? Ndarĩ hĩndĩ agacooka gũtũkenera?
8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
Wendo wake ũtathiraga-rĩ, nĩkũbuĩria ũbuĩrĩtie nginya tene? Kĩĩranĩro gĩake gĩgũtũũra gĩtahingĩte nginya tene?
9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
Kaĩ Mũrungu ariganĩirwo nĩkũiguanĩra tha? Kaĩ marakara make matũmĩte atige gũtugana?”
10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
Ngĩcooka ngĩĩciiria atĩrĩ, “Ũndũ ũyũ nĩguo ngwĩtiiria naguo: kũririkana mĩaka ya guoko kwa ũrĩo kwa Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno.”
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
Nĩngũririkana ciĩko cia Jehova; ĩĩ nĩguo, nĩngũririkana ciama ciaku cia tene.
12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
Ndĩrĩtaranagia mawĩra maku mothe, na ngecũũrania ũhoro wa ciĩko ciaku cia hinya.
13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
Njĩra ciaku, Wee Ngai, nĩ theru. Nĩ ngai ĩrĩkũ nene ta Ngai witũ?
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
Wee nĩwe Mũrungu ũrĩa ũringaga ciama; wonanagia ũhoti waku kũrĩ ndũrĩrĩ.
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
Nĩwakũũrire andũ aku na guoko gwaku kwa hinya, o acio njiaro cia Jakubu na Jusufu.
16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
Maaĩ nĩmakuonire, Wee Ngai, maaĩ macio maakuonire makĩigua guoya, nakuo kũrĩa kũriku mũno gũkĩĩnyogonda.
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
Matu mooiririe mbura, nacio ngwa ikĩruruma igũrũ guothe; heni ciahenũkire ikĩrathũka mĩena yothe
18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
Ngwa yaku yaiguĩkanire kĩhuhũkanio-inĩ, rũheni rwaku rũkĩmũrĩka thĩ yothe, nayo thĩ ĩkĩinaina na ĩgĩthingitha.
19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
Njĩra yaku yatuĩkanĩirie iria-inĩ, njĩra yaku ĩgĩtuĩkanĩria maaĩ-inĩ maingĩ, o na gũtuĩka makinya maku mationekire.
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Watongoririe andũ aku o ta ũrĩa mũrĩithi atongoragia rũũru, ũkĩmatongoria na guoko kwa Musa na kwa Harũni.

< Psalms 77 >