< Job 2 >

1 Ó sì tún di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá síwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn láti pe níwájú Olúwa.
Ningĩ nĩ kwarĩ mũthenya ũngĩ araika maathiire kũrũgama mbere ya Jehova, na Shaitani o nake agĩthiĩ hamwe nao kũrũgama mbere yake.
2 Olúwa sì bi Satani pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Satani sì dá Olúwa lóhùn pé, “Láti lọ síwá sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
Nake Jehova akĩũria Shaitani atĩrĩ, “Uuma kũ?” Nake Shaitani agĩcookeria Jehova atĩrĩ, “Nyuma kũriũnga thĩ o na gũcangacanga kuo kũndũ na kũndũ.”
3 Olúwa sì wí fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí ń ṣe olóòtítọ́ tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì kórìíra ìwà búburú, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di ìwà òtítọ́ rẹ̀ mu ṣinṣin, bí ìwọ tilẹ̀ ti dẹ mí sí i láti run ún láìnídìí.”
Ningĩ Jehova akĩũria Shaitani atĩrĩ, “Nĩũcũũranĩtie ũhoro wa ndungata yakwa Ayubu? Ũkoona atĩ kũu thĩ gũtirĩ mũndũ ũhaana take; ndarĩ ũcuuke na nĩ mũrũngĩrĩru, mũndũ mwĩtigĩri-Ngai na ũtheemaga maũndũ marĩa mooru. Ningĩ no arũmĩtie wĩhokeku wake, o na gũtuĩka nĩwaningĩrĩirie ndĩmwanange hatarĩ gĩtũmi.”
4 Satani sì dá Olúwa lóhùn wí pé, “Awọ fún awọ; àní ohun gbogbo tí ènìyàn ní, òun ni yóò fi ra ẹ̀mí rẹ̀.
Nake Shaitani agĩcookeria Jehova, akiuga atĩrĩ, “Gĩkonde kĩrĩhagwo na gĩkonde! Mũndũ no arute indo ciake ciothe nĩguo ahonokie muoyo wake.
5 Ṣùgbọ́n nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó tọ́ egungun rẹ̀ àti ara rẹ̀, bí kì yóò sì bọ́hùn ní ojú rẹ.”
No rĩrĩ, ta tambũrũkia guoko gwaku ũhutie mahĩndĩ na nyama cia mwĩrĩ wake, na ti-itherũ ndarĩ hĩndĩ ategũkũruma o ũthiũ-inĩ waku.”
6 Olúwa sì wí fún Satani pé, “Wò ó, ó ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n dá ẹ̀mí rẹ̀ sí.”
Nake Jehova akĩĩra Shaitani atĩrĩ, “No wega, rĩu arĩ moko-inĩ maku; no ndũkahutie muoyo wake.”
7 Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ Jobu ní oówo kíkankíkan láti àtẹ́lẹsẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Shaitani akiuma hau mbere ya Jehova, akĩnyamaria Ayubu na ironda ciarĩ na ruo mũno kuuma makinya ma magũrũ make nginya mũtwe.
8 Ó sì mú àpáàdì, ó fi ń họ ara rẹ̀, ó sì jókòó nínú eérú. (questioned)
Nake Ayubu akĩoya gacere ka nyũngũ ethũage nako, agĩikara thĩ harĩa haitagwo mũhu.
9 Nígbà náà ni aya rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ di ìwà òtítọ́ mú síbẹ̀! Bú Ọlọ́run, kí ó sì kú!”
Nake mũtumia wake akĩmũũria atĩrĩ, “Anga no ũrũmĩtie wĩhokeku waku o na rĩu? Ruma Ngai wĩkuĩre!”
10 Ṣùgbọ́n ó dá a lóhùn pé, “Ìwọ sọ̀rọ̀ bí ọ̀kan lára àwọn aṣiwèrè obìnrin ti í sọ̀rọ̀; há bà! Àwa yóò ha gba ìre lọ́wọ́ Ọlọ́run, kí a má sì gba ibi?” Nínú gbogbo èyí, Jobu kò fi ètè rẹ̀ ṣẹ̀.
Nake Ayubu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Wee ũraaria ta mũndũ-wa-nja mũkĩĩgu. Kaĩ turĩkĩamũkagĩra o maũndũ mega kuuma kũrĩ Ngai, na tũtiamũkĩre mathĩĩna?” Thĩinĩ wa maũndũ macio mothe-rĩ, Ayubu ndaigana kwĩhia thĩinĩ wa mĩario yake.
11 Nígbà tí àwọn ọ̀rẹ́ Jobu mẹ́ta gbúròó gbogbo ibi tí ó bá a, wọ́n wá, olúkúlùkù láti ibùjókòó rẹ̀; Elifasi, ara Temani àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama: nítorí pé wọ́n ti dájọ́ ìpàdé pọ̀ láti bá a ṣọ̀fọ̀, àti láti ṣìpẹ̀ fún un.
Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩrĩa arata atatũ a Ayubu, nĩo Elifazu ũrĩa Mũtemaani, na Bilidadi ũrĩa Mũshuhi, na Zofaru ũrĩa Mũnaamathi, maaiguire mathĩĩna marĩa mothe maakorete Ayubu-rĩ, makĩgĩa gĩathĩ, makiuma o mũndũ gwake na magĩcemania nĩguo mathiĩ makamũcakaithie o makĩmũhooreragia.
12 Nígbà tí wọ́n gbójú wọn wò ní òkèrè réré, tí wọ́n kò sì mọ̀ ọ́n, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sọkún: olúkúlùkù sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, wọ́n sì ku erùpẹ̀ sí ojú ọ̀run, wọ́n sì tẹ́ orí gbà á.
Rĩrĩa maamuonire marĩ o haraaya-rĩ, makĩrigwo nĩwe nĩ ũrĩa aahaanaga; makĩambĩrĩria kũrĩra maanĩrĩire, na magĩtembũranga nguo ciao, o na makĩĩhurĩria rũkũngũ mĩtwe.
13 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jókòó tì í ní inú erùpẹ̀ ní ọjọ́ méje ti ọ̀sán ti òru, ẹnikẹ́ni kò sì bá a sọ ọ̀rọ̀ kan, nítorí tí wọ́n ti rí i pé ìbànújẹ́ rẹ̀ pọ̀ jọjọ.
Ningĩ magĩcooka magĩikara thĩ hamwe nake matukũ mũgwanja, mũthenya na ũtukũ, na gũtirĩ mũndũ wamwaragĩria kiugo o na kĩmwe, nĩgũkorwo nĩmoonire atĩ kũnyamarĩka gwake kwarĩ kũnene mũno.

< Job 2 >