< Psalms 4 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi. Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́, ìwọ Ọlọ́run òdodo mi. Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi; ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
Az éneklőmesternek a neginóthra, Dávid zsoltára. Mikor kiáltok, hallgass meg engem, igazságomnak Istene; szorultságomban tág tért adtál nékem; könyörülj rajtam és halld meg az én imádságomat!
2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú? Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?
Emberek fiai! Meddig lesz gyalázatban az én dicsőségem? Meddig szerettek hiábavalóságot, és kerestek hazugságot? (Szela)
3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀; Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.
Tudjátok meg hát, hogy kedveltjévé választott az Úr; meghallja az Úr, ha hozzá kiáltok!
4 Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀, nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín, ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.
Haragudjatok, de ne vétkezzetek: beszéljetek szívetekkel a ti ágyasházatokban és csillapodjatok! (Szela)
5 Ẹ rú ẹbọ òdodo kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Igazságnak áldozatával áldozzatok, és bízzatok az Úrban.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?” Olúwa, jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,
Sokan mondják: Kicsoda láttat velünk jót? Hozd fel reánk arczodnak világosságát, oh Uram!
7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.
Nagyobb örömöt adsz így szívembe, mint a mikor sok az ő búzájok és boruk.
8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà, nítorí ìwọ nìkan, Olúwa, ni o mú mi gbé láìléwu.
Békességben fekszem le és legott elaluszom; mert te, Uram, egyedül adsz nékem bátorságos lakozást.

< Psalms 4 >