< Job 1 >

1 Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
Vala Úz földén egy ember, a kinek Jób vala a neve. Ez az ember feddhetetlen, igaz, istenfélő vala és bűn-gyűlölő.
2 A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
Születék pedig néki hét fia és három leánya.
3 Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
És vala az ő marhája: hétezer juh, háromezer teve és ötszáz igabarom és ötszáz szamár; cselédje is igen sok vala, és ez a férfiú nagyobb vala keletnek minden fiánál.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
Eljártak vala pedig az ő fiai egymáshoz és vendégséget szerzének otthon, kiki a maga napján. Elküldtek és meghívták vala az ő három hugokat is, hogy együtt egyenek és igyanak velök.
5 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
Mikor pedig a vendégség napjai sorra lejártak vala, elkülde értök Jób és megszentelé őket, és jóreggel felserkene és áldozik vala égőáldozattal mindnyájuk száma szerint; mert ezt mondja vala Jób: Hátha vétkeztek az én fiaim és gonoszt gondoltak az Isten ellen az ő szivökben! Így cselekedik vala Jób minden napon.
6 Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
Lőn pedig egy napon, hogy eljövének az Istennek fiai, hogy udvaroljanak az Úr előtt; és eljöve a Sátán is közöttök.
7 Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
És monda az Úr a Sátánnak: Honnét jösz? És felele a Sátán az Úrnak és monda: Körülkerültem és át meg át jártam a földet.
8 Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
És monda az Úr a Sátánnak: Észrevetted-é az én szolgámat, Jóbot? Bizony nincs hozzá hasonló a földön: feddhetetlen, igaz, istenfélő, és bűngyűlölő.
9 Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
Felele pedig az Úrnak a Sátán, és monda: Avagy ok nélkül féli-é Jób az Istent?
10 “Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
Nem te vetted-é körül őt magát, házát és mindenét, a mije van? Keze munkáját megáldottad, marhája igen elszaporodott e földön.
11 Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
De bocsássad csak rá a te kezedet, verd meg mindazt, a mi az övé, avagy nem átkoz-é meg szemtől-szembe téged?!
12 Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
Az Úr pedig monda a Sátánnak: Ímé, mindazt, a mije van, kezedbe adom; csak ő magára ne nyujtsd ki kezedet. És kiméne a Sátán az Úr elől.
13 Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
Lőn pedig egy napon, hogy az ő fiai és leányai esznek és bort isznak vala az ő elsőszülött bátyjoknak házában.
14 oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
És követ jöve Jóbhoz, és monda: Az ökrök szántanak, a szamarak pedig mellettök legelésznek vala.
15 àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
De a Sabeusok rajtok ütének és elhajták azokat, a szolgákat pedig fegyverrel ölék meg. Csak én magam szaladék el, hogy hírt adjak néked.
16 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
Még szól vala ez, mikor jöve egy másik, és monda: Istennek tüze esék le az égből, és megégeté a juhokat és a szolgákat, és megemészté őket. Csak én magam szaladék el, hogy hírt adjak néked.
17 Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
Még ez is szól vala, mikor jöve egy másik, és monda: A Káldeusok három csapatot alkotának és ráütének a tevékre, és elhajták azokat; a szolgákat pedig fegyverrel ölék meg, csak én magam szaladék el, hogy hírt adjak néked.
18 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
Még ez is szól vala, mikor jöve egy másik, és monda: A te fiaid és leányaid esznek és bort isznak vala az ő elsőszülött bátyjoknak házában;
19 Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
És ímé nagy szél támada a puszta felől, megrendíté a ház négy szegeletét, és rászakada az a gyermekekre és meghalának. Csak én magam szaladék el, hogy hírt adjak néked.
20 Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
Akkor felkele Jób, megszaggatá köntösét, megberetválá a fejét, és a földre esék és leborula.
21 wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
És monda: Mezítelen jöttem ki az én anyámnak méhéből, és mezítelen térek oda, vissza. Az Úr adta, az Úr vette el. Áldott legyen az Úrnak neve!
22 Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.
Mindezekben nem vétkezék Jób, és Isten ellen semmi illetlent nem cselekedék.

< Job 1 >