< Psalms 37 >

1 Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
Thaburi ya Daudi Tigaga gũthĩĩnĩka ngoro nĩ ũndũ wa andũ arĩa mekaga ũũru, o na kana ũiguage ũiru nĩ ũndũ wa arĩa mekaga mahĩtia;
2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
nĩgũkorwo acio makaahooha o narua o ta ũrĩa nyeki ĩhoohaga, na makue narua o ta ũrĩa riya rĩhoohaga rĩamunywo.
3 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Wĩhoke Jehova na wĩkage wega; tũũra bũrũri-inĩ ũkenagĩra ũrĩithio wa thayũ.
4 Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
Ĩkaga maũndũ ma gũkenia Jehova, na nĩarĩkũhingagĩria merirĩria ma ngoro yaku.
5 Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Rekagĩrĩria Jehova njĩra yaku; mwĩhokage o we, nake nĩarĩĩkaga maũndũ maya:
6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
Nĩarĩtũmaga ũthingu waku ware o ta rũciinĩ, nakĩo kĩhooto gĩa ciira waku kĩare o ta riũa rĩa mũthenya barigici.
7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
Hoorera mbere ya Jehova na ũmweterere ũtegũthethũka; ndũgathĩĩnĩke ngoro rĩrĩa andũ magaacĩra mĩthiĩre-inĩ yao, rĩrĩa mekũhingia mathugunda mao ma gwĩka ũũru.
8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Tigaga kũrakara na wĩrigagĩrĩrie mangʼũrĩ; tigaga gũthĩĩnĩka ngoro, tondũ ũndũ ũcio no ũtũme wĩke ũũru.
9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
Nĩgũkorwo andũ ooru nĩmakaniinwo, no arĩa mehokete Jehova nĩmakagaya bũrũri.
10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
No kahinda kanini, arĩa aaganu mage kuoneka rĩngĩ; o na mũngĩmacaria, mũtingĩmoona.
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
No arĩa ahooreri nĩo makaagaya bũrũri, na matũũre makenete nĩkũingĩhĩrwo nĩ thayũ.
12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
Andũ arĩa aaganu mathugundaga mokĩrĩre andũ arĩa athingu, na makamahagaranĩria magego;
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
no Mwathani athekagĩrĩra andũ acio aaganu, nĩgũkorwo nĩoĩ mũthenya wao nĩũrooka.
14 Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
Andũ arĩa aaganu macomorete hiũ cia njora, na makageeta ũta nĩguo maniine mũndũ ũrĩa mũthĩĩni na mũbatari, na moorage andũ arĩa njĩra ciao irũngĩrĩirie.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
No hiũ icio ciao cia njora igaatheeca ngoro ciao ene, na mota mao moinangwo.
16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
Nĩ kaba kĩndũ kĩnini kĩrĩ na andũ arĩa athingu, gũkĩra ũtonga mũingĩ wa andũ aaganu;
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
nĩgũkorwo hinya wa andũ arĩa aaganu nĩũkaniinwo, no Jehova atiiragĩrĩra andũ arĩa athingu.
18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
Matukũ ma andũ arĩa matarĩ ũcuuke nĩmooĩo nĩ Jehova, na igai rĩao rĩgũtũũra nginya tene.
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
Hĩndĩ ya mwanangĩko matikoona ũũru; na hĩndĩ ya ngʼaragu magaakorwo na irio cia kũigana.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
No andũ arĩa aaganu nĩmagathira: Thũ cia Jehova igaathira ta ũrĩa ũthaka wa mĩgũnda ũthiraga, nĩikabuĩria, ibuĩrie o ta ndogo.
21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
Andũ arĩa aaganu makoombaga na matirĩhaga, no arĩa athingu maheanaga na ũtaana;
22 nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
andũ arĩa Jehova arathimĩte nĩmakagaya bũrũri, no arĩa arumĩte nĩmakaniinwo.
23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
Jehova angĩkenio nĩ mũthiĩre wa mũndũ, atũmaga makinya make marũme wega;
24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
o na angĩhĩngwo, ndangĩgũa, nĩgũkorwo Jehova amũnyiitagĩrĩra na guoko gwake.
25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
Ndaarĩ mũnini, na rĩu ndĩ mũkũrũ, no ndirĩ ndoona andũ arĩa athingu matiganĩirio, kana ciana ciao ikĩhooya irio.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
Hĩndĩ ciothe makoragwo marĩ ataana, na makombanagĩra matekwenda uumithio; ciana ciao nĩ ikaarathimwo.
27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
Theemaga ũũru, na wĩkage wega, nawe ũtũũre bũrũri-inĩ nginya tene.
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
Nĩgũkorwo Jehova endete o kĩhooto, na ndagatiganĩria arĩa ake ehokeku. Acio megũtũũra magitĩirwo nginya tene, no ciana cia arĩa aaganu nĩikaniinwo.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
Andũ arĩa athingu nĩo makaagaya bũrũri, na matũũre kuo nginya tene.
30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
Kanua ka mũndũ mũthingu gatumũkaga ndeto cia ũũgĩ, naruo rũrĩmĩ rwake rũkaaria kĩhooto.
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
Watho wa Ngai wake ũrĩ o ngoro-inĩ yake; makinya make matingĩtenderũka.
32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
Andũ arĩa aaganu maikaraga moheirie arĩa athingu, magĩcaria o ũrĩa mangĩmooraga;
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
no Jehova ndakamatiganĩria moko-inĩ ma andũ acio aaganu, kana areke matuĩrwo atĩ nĩ ehia rĩrĩa magaaciirithio.
34 Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
Etagĩrĩra Jehova na ũrũmagĩrĩre njĩra yake. Nĩagagũtũũgĩria nĩguo ũgae bũrũri; rĩrĩa andũ arĩa aaganu makaaniinwo-rĩ, wee nĩũkeyonera ũndũ ũcio.
35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
Nĩnyonete mũndũ mwaganu na mũndũ ũtarĩ tha agaacĩire ta mũtĩ mũruru ũrĩ o imerero-inĩ rĩaguo,
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
no thuutha wa kahinda o kanini akĩehera, akĩaga gũkorwo ho rĩngĩ; o na gũtuĩka nĩndamũcaririe, ndiigana kũmuona.
37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
Cũrania ũhoro wa mũndũ ũrĩa ũtarĩ ũcuuke, na ũrore ũrĩa mũrũngĩrĩru, ũhoro wake wa matukũ marĩa magooka nĩ ũhoro wa thayũ.
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
No rĩrĩ, andũ arĩa ehia othe nĩmakaniinwo; no andũ arĩa aaganu mũthia wao nĩ kũũragwo makooragwo.
39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
Ũhonokio wa andũ arĩa athingu uumaga kũrĩ Jehova; we nĩwe kĩĩhitho kĩao kĩa hinya hĩndĩ ya mathĩĩna.
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
Jehova nĩamateithagia na akamateithũra; amateithũraga kuuma kũrĩ andũ arĩa aaganu na akamahonokia, tondũ moragĩra harĩ we.

< Psalms 37 >