< Psalms 3 >

1 Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu. Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí! Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
Dawut ɵz oƣli Abxalomdin ⱪeqip yürgǝn künlǝrdǝ yazƣan küy: — I Pǝrwǝrdigar, meni ⱪistawatⱪanlar nǝⱪǝdǝr kɵpiyip kǝtkǝn, Mǝn bilǝn ⱪarxilixiwatⱪanlar nemidegǝn kɵp!
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé “Ọlọ́run kò nígbà á là.” (Sela)
Nurƣunlar mǝn toƣruluⱪ: — «Hudadin uningƣa ⱨeq nijat yoⱪtur!» deyixiwatidu. (Selaⱨ)
3 Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa; ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
Biraⱪ Sǝn, i Pǝrwǝrdigar, ǝtrapimdiki ⱪalⱪandursǝn; Xan-xǝripim ⱨǝm beximni yɵligüqidursǝn!
4 Olúwa ni mo kígbe sókè sí, ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. (Sela)
Awazim bilǝn mǝn Pǝrwǝrdigarƣa nida ⱪilimǝn, U muⱪǝddǝs teƣidin ijabǝt beridu. (Selaⱨ)
5 Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn; mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.
Mǝn bolsam yattim, uhlidim; Oyƣandim, qünki Pǝrwǝrdigar manga yar-yɵlǝk bolidu.
6 Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.
Meni ⱪorxap sǝp tüzgǝn tümǝnligǝn adǝmlǝr bolsimu, Mǝn ulardin ⱪorⱪmaymǝn!
7 Dìde, Olúwa! Gbà mí, Ọlọ́run mi! Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n; kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.
I Pǝrwǝrdigar, ornungdin tur! Meni ⱪutⱪuz, i Hudayim! Mening barliⱪ düxmǝnlirimning tǝstikigǝ salƣaysǝn; Rǝzillǝrning qixlirini qeⱪiwǝtkǝysǝn!
8 Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá. Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. (Sela)
Nijatliⱪ bolsa Pǝrwǝrdigardindur; Bǝrikiting Ɵz hǝlⱪingdǝ bolsun! (Selaⱨ)

< Psalms 3 >