< Psalms 21 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
E IEHOVA, e hauoli aku ke alii i kou mana; Nani hoi kona olioli ana i kou ola.
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
Ua haawi mai oe ia ia i ka mea a kona naau i makemake ai; Aole oe i hoole i ka mea a kona lehelehe i noi aku ai. (Sila)
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
A, ua haawi e mai oe ia ia i pomaikai i ka pono; Ua kau mai oe i ka lei gula maemae maluna iho o kona poo.
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
Ua noi aku oia ia oe i ola, nau no ia i haawi mai nona; O ke ola loa i ka manawa pau ole.
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
He nui wale kona nani i kou ola; O ka mahalo, a me ka hanohano kau i kau mai ai maluna iho ona.
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
Ua hoopomaikai io mau loa oe ia ia; Ua hoohauoli loa oe ia ia i kou maka.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
No ka mea, na hilinai aku ke alii ia Iehova, No ka lokomaikai o ka Mea kiekie loa e kulanalana ole ai ia.
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
E loaa no i kou lima kou mau enemi a pau; E loaa no i kou lima akau ka poe inaina ia oe.
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
E hoohalike no oe ia lakou me he umu ahi la i kou wa e huhu ai; E ale no Iehova ia lakou i kona inaina, e pau hoi lakou i ke ahi.
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
Nau no ka lakou hua e luku aku, mai ka honua aku, A me ka lakou mamo, mai waena aku o na keiki a kanaka.
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
No ka mea, ua hoopalahalaha lakou i ka ino nou; Ua kuka lakou i ka manao hewa, aole hoi i hiki.
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
Nolaila, e hoohuli mai oe i ko lakou kua; Ke hoomakaukau oe i na pua i kau mau kaula, i ku pono i ko lakou alo.
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
E hapaiia'ku oe, e Iehova, i kou ikaika; E oli no hoi makou me ka hoolea aku i kou mana.

< Psalms 21 >