< Psalms 20 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
E HOOLOHE mai o Iehova ia oe i ka la popilikia; I ola oe i ka inoa o ke Akua no Iakoba.
2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
Mai kona keenakapu mai e hoouna mai ai oia i kou mea nana e alu; Mai Ziona mai e kokua mai ai oia ia oe.
3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
E hoomanao mai hoi i kau mau mohai a pau; A e hoopono mai hoi i kau mohai kuni. (Sila)
4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
E haawi mai hoi e like me kou naau iho, E hooko mai hoi i kou manao a pau.
5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
I kou ola e hauoli ai makou, A i ka inoa o ko kakou Akua e kau ai kakou i ka hae: E ae mai hoi o Iehova i kau pule a pau.
6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Ano ua ike au, ua hoola o Iehova i kona mea i poniia; Ma kona lani hoano no ia e hoolohe mai ai ia ia, Me ka mana o kona lima akau e ola'i.
7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
Ma na kaakaua kekahi poe, ma na lio kekahi i manao ai; Aka, e hoomanao kakou i ka inoa o Iehova o ko kakou Akua.
8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
Ua emi lakou, ua haule ilalo; Aka, ua ala mai nei makou a ku pono iluna.
9 Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!
E hoola mai, e Iehova; E hoolohe mai ke alii ia makou i ko makou kahea ana.

< Psalms 20 >