< Psalms 16 >

1 Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
Écrit de David. Garde-moi, Seigneur, car j'ai mis en toi mon espérance.
2 Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
J'ai dit au Seigneur: Tu es mon Seigneur, et tu n'as nul besoin de mes biens.
3 Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
Quant aux saints qui sont sur la terre, il a fait éclater toutes ses volontés pour eux.
4 Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
Leurs infirmités se sont multipliées, et cependant ils ont couru rapidement; je ne rassemblerai plus leurs synagogues de sang; et de mes lèvres je ne mentionnerai pas leur nom.
5 Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
Le Seigneur est la part de mon héritage et de mon calice; c'est toi, Seigneur, qui me restitueras mon héritage.
6 Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
Les cordeaux sont tombés pour moi aux meilleures places; car mon héritage est excellent.
7 Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
Je bénirai le Seigneur, qui m'a donné l'intelligence; mes désirs aussi me pressaient vivement jusque dans la nuit même.
8 Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
Je n'ai cessé de voir devant moi le Seigneur; car il se tient à ma droite, pour que je ne sois pas ébranlé.
9 Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
C'est pourquoi mon cœur s'est réjoui, ma langue a tressailli d'allégresse, et ma chair se reposera dans l'espérance:
10 nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol h7585)
Parce que tu ne laisseras pas mon âme aux enfers; tu ne permettras pas que ton Saint voie la corruption. (Sheol h7585)
11 Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Tu m'as fait connaître les voies de la vie; tu me rempliras de joie par ton aspect; des délices éternelles sont à ta droite.

< Psalms 16 >