< Psalms 15 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, ta ni yóò máa ṣe àtìpó nínú àgọ́ rẹ? Ta ni yóò máa gbé ní òkè mímọ́ rẹ?
Psaume de David. Seigneur, qui habitera dans ton tabernacle? Qui reposera sur ta montagne sainte?
2 Ẹni tí ń rìn déédé tí ó sì ń sọ òtítọ́, láti inú ọkàn rẹ̀;
Celui qui marche dans l'innocence et qui opère la justice; qui dit la vérité en son cœur
3 tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, tí kò ṣe ibi sí aládùúgbò rẹ̀ tí kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí ẹnìkejì rẹ̀,
Et dont la langue n'a jamais trompé; qui n'a point fait tort à son prochain, et n'a point cru à la diffamation contre ses proches.
4 ní ojú ẹni tí ènìyànkénìyàn di gígàn ṣùgbọ́n ó bọ̀wọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, ẹni tí ó búra sí ibi ara rẹ̀ àní tí kò sì yípadà,
Le méchant n'est rien à ses yeux; il honore ceux qui craignent le Seigneur; s'il fait un serment à son prochain, il ne le trompe pas.
5 tí ó ń yá ni lówó láìsí èlé tí kò sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lòdì sí aláìlẹ́ṣẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe èyí ni a kì yóò mì láéláé.
Il n'a point prêté son argent à usure; il n'a point accepté de dons contre l'innocent. Celui qui fait ces choses ne sera point ébranlé dans l'éternité.

< Psalms 15 >