< Psalms 140 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
Mai marelui muzician, un psalm al lui David. Scapă-mă, DOAMNE, de omul rău; păzește-mă de omul violent,
2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
Care își închipuie ticăloșii în inimă; continuu se adună pentru război.
3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
Și-au ascuțit limbile ca un șarpe; veninul viperei este sub buzele lor. (Selah)
4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
Păzește-mă, DOAMNE, de mâinile celui stricat; protejează-mă de omul violent, de cei care au plănuit să doboare umbletele mele.
5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
Cei mândri mi-au ascuns o capcană și funii; au întins o plasă pe cale; mi-au pus curse. (Selah)
6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Eu i-am spus DOMNULUI: Tu ești Dumnezeul meu, ascultă vocea cererilor mele, DOAMNE.
7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
DUMNEZEULE, Doamne, tăria salvării mele, mi-ai acoperit capul în ziua bătăliei.
8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
Nu împlini, DOAMNE, dorințele celui stricat; nu duce mai departe planul lui stricat, pentru a nu se înălța. (Selah)
9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Cât despre capul celor ce mă înconjoară, să îi acopere ticăloșia propriilor lor buze.
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
Să cadă cărbuni aprinși peste ei; să fie aruncați în foc; în gropi adânci, ca să nu se ridice din nou.
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
Nu lăsa pe bărbatul vorbitor de rău să fie întemeiat pe pământ; răul va vâna pe omul violent pentru a-l doborî.
12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
Știu că DOMNUL va susține cauza celui nenorocit și dreptul celor săraci.
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
Da, cei drepți vor aduce mulțumiri numelui tău; cei integri vor locui în prezența ta.

< Psalms 140 >