< Psalms 108 >
1 Orin. Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run, ọkàn mi dúró ṣinṣin èmi ó máa kọrin, èmi ó máa fi ọkàn mi kọrin.
Preparado está o meu coração, ó Deus; cantarei e direi salmos até com a minha glória.
2 Jí ohun èlò orin àti haapu! Èmi ó jí ní kùtùkùtù,
Desperta-te, saltério e harpa; eu mesmo despertarei ao romper da alva.
3 èmi ó yìn ọ́, Olúwa, nínú àwọn orílẹ̀-èdè, èmi ó kọrin rẹ nínú àwọn ènìyàn.
Louvar-te-ei entre os povos, Senhor, e a ti cantarei salmos entre as nações.
4 Nítorí tí o tóbi ní àánú rẹ ju àwọn ọ̀run lọ àti òdodo rẹ dé àwọsánmọ̀.
Porque a tua benignidade se estende até aos céus, e a tua verdade chega até às mais altas nuvens.
5 Gbé ara rẹ ga, Ọlọ́run, lórí àwọn ọ̀run, àti ògo rẹ lórí gbogbo ayé.
Exalta-te sobre os céus, ó Deus, e a tua glória sobre toda a terra,
6 Kí a sì lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ là; fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ìgbàlà, kí o sì dá mi lóhùn
Para que sejam livres os teus amados: salva-nos com a tua dextra, e ouve-nos.
7 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò yọ̀, èmi yóò pín Ṣekemu, èmi yóò sì wọn àfonífojì Sukkoti kúrò.
Deus falou na sua santidade: eu me regozijarei; repartirei a Sichem, e medirei o vale de Succoth.
8 Gileadi ni tèmi, Manase ni tèmi, Efraimu ni ìbòrí mi, Juda ni olófin mi,
Meu é Galaad, meu é Manassés; e Ephraim a força da minha cabeça, Judá o meu legislador,
9 Moabu sì ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ni èmi ó bọ́ bàtà mi sí, lórí òkè Filistia ni èmi yóò hó ìhó ayọ̀.”
Moab o meu vaso de lavar: sobre Edom lançarei o meu sapato, sobre a Palestina jubilarei.
10 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi? Ta ni yóò sìn mí wá sí Edomu?
Quem me levará à cidade forte? Quem me guiará até Edom?
11 Ìwọ Ọlọ́run ha kọ́, ìwọ tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀. Ọlọ́run ìwọ kì yóò bá àwọn jagunjagun wa jáde mọ́.
Porventura não serás tu, ó Deus, que nos rejeitaste? E não sairás, ó Deus, com os nossos exércitos?
12 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ nínú ìpọ́njú, nítorí ìrànlọ́wọ́ ènìyàn asán ni.
Dá-nos auxílio para sair da angústia, porque vão é o socorro da parte do homem.
13 Nípasẹ̀ Ọlọ́run ni àwa ó ṣe akin nítorí òun ó tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
Em Deus faremos proezas, pois ele calcará aos pés os nossos inimigos.