< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Rendez grâce à Yahvé! Invoquez son nom! Faites connaître ses actions parmi les peuples.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Chantez-lui, chantez-lui des louanges! Racontez toutes ses œuvres merveilleuses.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Gloire à son saint nom. Que le cœur de ceux qui cherchent Yahvé se réjouisse.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Recherchez Yahvé et sa force. Cherchez son visage pour toujours.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Rappelez-vous les merveilles qu'il a faites: ses merveilles, et les jugements de sa bouche,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
vous, descendants d'Abraham, son serviteur, vous, enfants de Jacob, ses élus.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Il est Yahvé, notre Dieu. Ses jugements sont dans toute la terre.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Il s'est souvenu de son alliance pour toujours, la parole qu'il a commandée à mille générations,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
l'alliance qu'il a conclue avec Abraham, son serment à Isaac,
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
et l'a confirmé à Jacob pour une loi; à Israël pour une alliance éternelle,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
en disant: « Je vous donnerai le pays de Canaan, le lot de votre héritage, »
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
alors qu'ils n'étaient qu'un petit nombre d'hommes, oui, très peu, et des étrangers en son sein.
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Ils allaient de nation en nation, d'un royaume à un autre peuple.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Il n'a permis à personne de leur faire du mal. Oui, il a réprimandé les rois pour leur bien,
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
« Ne touchez pas à mes oints! Ne faites pas de mal à mes prophètes! »
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Il a appelé la famine sur le pays. Il a détruit les réserves de nourriture.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Il envoya un homme devant eux. Joseph a été vendu comme esclave.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
On lui a meurtri les pieds avec des entraves. Son cou a été mis aux fers,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
jusqu'au moment où sa parole s'est accomplie, et la parole de Yahvé lui a donné raison.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Le roi l'envoya et le libéra, même le chef des peuples, et le laisser libre.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Il l'a fait seigneur de sa maison, et le maître de toutes ses possessions,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
pour discipliner ses princes à son gré, et d'enseigner la sagesse à ses aînés.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Israël aussi est venu en Égypte. Jacob a vécu dans le pays de Ham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Il a beaucoup augmenté son peuple, et les a rendus plus forts que leurs adversaires.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Il a détourné leur cœur pour qu'ils haïssent son peuple, pour conspirer contre ses serviteurs.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Il envoya Moïse, son serviteur, et Aaron, qu'il avait choisi.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Ils faisaient des miracles au milieu d'eux, et des merveilles dans le pays de Ham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Il a envoyé les ténèbres, et il a rendu les ténèbres. Ils ne se sont pas rebellés contre ses paroles.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Il a changé leurs eaux en sang, et ont tué leurs poissons.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Leur terre grouillait de grenouilles, même dans les chambres de leurs rois.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Il parla, et des nuées de mouches vinrent, et des poux dans toutes leurs frontières.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Il leur a donné de la grêle en guise de pluie, avec des éclairs dans leur pays.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Il a frappé leurs vignes et aussi leurs figuiers, et ont brisé les arbres de leur pays.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Il parla, et les sauterelles vinrent avec les sauterelles, sans nombre.
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Ils ont dévoré toutes les plantes de leur pays, et ont mangé le fruit de leur sol.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Il frappa aussi tous les premiers-nés de leur pays, les premiers fruits de toute leur virilité.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Il les fit sortir avec de l'argent et de l'or. Il n'y avait pas une seule personne faible parmi ses tribus.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
L'Égypte se réjouit de leur départ, car la peur d'eux était tombée sur eux.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Il a étendu un nuage pour le couvrir, le feu pour donner de la lumière dans la nuit.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Ils ont demandé, et il a apporté des cailles, et les a rassasiés avec le pain du ciel.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Il ouvrit le rocher, et des eaux jaillirent. Ils coulaient comme un fleuve dans les endroits secs.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Car il s'est souvenu de sa sainte parole, et Abraham, son serviteur.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Il a fait sortir son peuple avec joie, son choix avec le chant.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Il leur a donné les terres des nations. Ils ont pris le travail des peuples en possession,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
afin qu'ils gardent ses statuts, et observez ses lois. Louez Yah!

< Psalms 105 >