< Psalms 101 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
Un psaume de David. Je chanterai la bonté et la justice. A toi, Yahvé, je chanterai des louanges.
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
Je veillerai à mener une vie irréprochable. Quand viendras-tu me voir? Je marcherai dans ma maison avec un cœur irréprochable.
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
Je ne mettrai pas de choses viles devant mes yeux. Je déteste les actes des hommes sans foi. Ils ne s'accrocheront pas à moi.
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
Un cœur pervers sera loin de moi. Je ne veux rien avoir à faire avec le mal.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
Je ferai taire celui qui calomnie secrètement son prochain. Je ne tolérerai pas celui qui est arrogant et prétentieux.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
Mes yeux se porteront sur les fidèles du pays, pour qu'ils puissent habiter avec moi. Celui qui marche d'une manière parfaite, il me servira.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
Celui qui pratique la tromperie n'habitera pas dans ma maison. Celui qui dit des mensonges ne sera pas établi devant mes yeux.
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Matin après matin, je détruirai tous les méchants du pays, pour exterminer de la cité de Yahvé tous les artisans de l'iniquité.

< Psalms 101 >