< Philippians 2 >
1 Bí ìwọ bá ní ìmúlọ́kànle nítorí pé ìwọ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Kristi, bi ìtùnú kan bá wà nínú ìfẹ́ rẹ̀, bí ìdàpọ̀ Ẹ̀mí kan bá wà, bí ìyọ́nú àti ìṣeun bá wà,
no nekangka bi kwannek wiri no birum neri wiri wi wo cwika netiyeri, no mwer ka-ngka duwe mor yuwa tangbe wucake wiri, no cire duwe ka-nge bunangka wiri,
2 síbẹ̀ ẹ mú ayọ̀ mi kún nínú ìṣọ̀kan yín, nípa ìfẹ́ kan náà, wíwà ní ẹ̀mí kan náà àti ète kan náà.
ko dok bilantum mini bo a dim, nawo ka yilam nero wiine, kom kicwika wiin, ko mwerka-ngum mor yuwako wucake kom ki dige ka yõ kabawiin.
3 Ẹ má ṣe ohunkóhun nínú ìlépa ara tàbí ògo asán, ṣùgbọ́n ní ìrẹ̀lẹ̀ ọkàn kí olúkúlùkù ro àwọn ẹlòmíràn sí ẹni ti ó sàn ju òun lọ.
kom mare diger ki cwika duwe kaka'a diger bi boler, nyori ki taka duwe, tu tang ne nube cin lã nen.
4 Kí olúkúlùkù yín má ṣe ro ohun ti ara rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ti ẹlòmíràn pẹ̀lú.
kom tore ka dike kom cwitiye koni, nyori kom to dige kangumbo cwitiyeu.
5 Nínú ìbáṣepọ̀ yin pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, ẹ ni irú ìlépa ọkàn náà bí ti Kristi Jesu.
ki nyimom wori ki bwikimi, buro mor kiristi Yeesu.
6 Ẹni tí, bí o tilẹ̀ jẹ́ ìrísí Ọlọ́run, kò kà á sí ohun tí ìbá fi ìwọra gbámú láti bá Ọlọ́run dọ́gba.
wori yi yim na kwama dila tũbo dor cerowiin na kwama.
7 Ṣùgbọ́n ó bọ́ ògo rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú àwọ̀ ìránṣẹ́, a sì ṣe é ni àwòrán ènìyàn.
nyori cin tũ dor cero na cang. ci ki bwi nifire, cin tũ dor cero canga cin cerkangu na nifir.
8 Ó sì wà ní àwòrán ènìyàn, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, o sì tẹríba títí de ojú ikú, àní ikú lórí àgbélébùú.
con cukum dor ki co cero, cin yilam ki ne duri wo yo yaken ki co bware, bwaro wo dor bwatiye reu,
9 Nítorí náà, Ọlọ́run ti gbé e ga sí ipele tí ó ga jùlọ, ó sì ti fi orúkọ kan ti ó borí gbogbo orúkọ fún un,
nyori kwama neco duktankaku dur, con neco dendo la den gwamme.
10 pé ni orúkọ Jesu ni kí gbogbo eékún máa wólẹ̀, ní ọ̀run, àti ní orí ilẹ̀ ayé àti ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
ci ma wureu, na nyori mor dene Yeesu dwendo gwam an cun-cunge, dwen nobo wo kwamau, ka-nge wo dor bitinereu ka-nge wo mor bitineu
11 àti pé kí gbogbo ahọ́n jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi ni Olúwa, fún ògo Ọlọ́run Baba.
ca mawo na biyendo gwam, na toki ki, “Yeesu co kiristi ka-nge Teluwe ker duktongka kwama Teu.
12 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ń gbọ́rọ̀ nígbà gbogbo, kì í ṣe nígbà ti mo wà lọ́dọ̀ yín nìkan, ṣùgbọ́n pàápàá nísinsin yìí tí èmi kò sí ni àárín yín, ẹ máa ṣiṣẹ́ ìgbàlà yín yọrí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì,
nyori kom keb mibo mi cwitiye, nawo ki ne durti ki ca tecceu nuwen, la can a lã nyo mi maniyeu. ki do fangka kime ko ki tai ka-nge, kwama bwiyek.
13 nítorí pé Ọlọ́run ni ó n ṣiṣẹ́ nínú yín, láti fẹ́ àti láti ṣiṣẹ́ fún ète rere rẹ̀.
wo kwama ma nangen ti more kime ki cwika cek ka-nge nuwa ka luma ce ken.
14 Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láìsí ìkùnsínú àti ìjiyàn.
kom ma diger gwam kebo ki fwenna kaka kwob kanka.
15 Kí ẹ̀yin lè jẹ́ aláìlẹ́gàn àti oníwà mímọ́, ọmọ Ọlọ́run, aláìlábàwọ́n, láàrín oníwà wíwọ́ àti alárékérekè orílẹ̀-èdè láàrín àwọn ẹni tí a ń rí yín bí ìmọ́lẹ̀ ní ayé.
nyori na kom yilam kom man ki kwama man ki diger bitorek ka-nge bilengke, bi bei kwama man ki diger bitorektiber kaldo wo bwira nyonlangum-nyonlangeu, woro ka yilam kira tibati mor kale.
16 Bí ẹ sì ṣe di ọ̀rọ̀ ìyè mú gírígírí, kí èmi lè ṣògo ni ọjọ́ Kristi pé èmi kò sáré lásán, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ṣe làálàá lásán.
kom tam ker dume, na nyori ki bi diye kiristi na yilam ki nyial ma cwa bo cwak ka-ge nangen koni.
17 Ṣùgbọ́n, bí a tilẹ̀ ń dà mí bí ọtí-ìrúbọ sórí ẹbọ iṣẹ́ ìsìn ìgbàgbọ́ yín, inú mi dùn, mo sì ń bá gbogbo yín yọ̀ pẹ̀lú.
no mwenno ci yumyeti na nuwang twika ka-nge nangen bilen keret di, miki fwor nerek ka-nge bilengka kimen gwam.
18 Bákan náà ni kí ẹ̀yin máa yọ̀, kí ẹ sì máa bá mi yọ̀ pẹ̀lú.
nyo takeu, kom ken nuwa luma, naki bilangi ka-nge mo.
19 Mo ni ìrètí nínú Jesu Olúwa, láti rán Timotiu sí yín ni àìpẹ́ yìí, kí èmi pẹ̀lú lè ni ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí mo bá gbúròó yín.
nyori muki nyo-neri Teluwe Yeesu nin in twom Timoti kimen kutang bo, na fiya bi kwamar neret no nuwa dige dor kimerdi.
20 Nítorí èmi kò ni ẹlòmíràn tí ó dàbí rẹ̀, tí yóò máa fi tinútinú ṣe àníyàn yín.
mi mangki nii na co, wori ki bi cwom kwa kom ti ki neri.
21 Nítorí gbogbo wọn ni ó tọ́jú nǹkan ti ara wọn, kì í ṣe àwọn nǹkan ti Jesu Kristi.
wori digero dor cire koni ci nyime kebo digero wo na Yeesu kiristi.
22 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin mọ̀ pé Timotiu pegedé, gẹ́gẹ́ bí ọmọ lọ́dọ̀ baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ti ń bá mi ṣiṣẹ́ pọ̀, nínú iṣẹ́ ìyìnrere.
ka nyimom yora ceko, wori na bwe te nin, con mamen nangen mor fulen kere.
23 Nítorí náà, mo ní ìrètí láti rán sí yín ní àìpẹ́ tí mo bá wòye bí yóò ti rí fún mi.
nyori mi yo nerti na twom co kimen non to dige a yakenti fo ka-nge mer.
24 Ṣùgbọ́n mo ní gbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa, pé èmi tìkára mi pẹ̀lú yóò wá ní àìpẹ́.
miki bi kwamer neret mor Teluwe, mo ki bwimi man bou kutang bo.
25 Mo kà á sí pé n kò lè ṣàìrán Epafiroditu arákùnrin mi sí yín, àti olùbáṣiṣẹ́ pọ̀ mi, àti ọmọ-ogun ẹlẹgbẹ́ mi, ìránṣẹ́ yín pẹ̀lú, tí ẹ rán láti ṣè ránṣẹ́ fún mi nínú àìní mi.
min tõ tam yo twom Abafaroditu a wajenku. con ka-nge far nangenne ka-nge far kwene ka-nge nii tome ka-nge canga kime dor dige mi cwitiye.
26 Nítorí tí ọkàn rẹ̀ fà sí gbogbo yín, ó sì kún fún ìbànújẹ́, nítorí tí ẹ̀yin gbọ́ pé ó ṣe àìsàn.
wori con kung ner dor kimer, na co ya kimen gwam, wori kom nuwa ki co nuwa bo luma.
27 Nítòótọ́ ni ó ti ṣe àìsàn títí dé ojú ikú, ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti ṣàánú fún un; kì í sì í ṣe fún òun nìkan, ṣùgbọ́n fún èmi pẹ̀lú kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lórí ìbànújẹ́.
ki cwom ca nuwabo luma, con dadom bwar, la kwama cii dor cero, kebo co ka-nge mo, nyori nan fiyare bwiraka nere dor bwiraka nerek.
28 Nítorí náà ni mo ṣe ní ìtara láti rán an, pé nígbà tí ẹ̀yin bá sì tún rí i, kí ẹ̀yin lè yọ̀ àti kí ìkáyà sókè mi lè dínkù.
nyori miki kuru ducce, twom co no komto co tak ri kan bilangi, mo keneu ner mure an daken.
29 Nítorí náà, ẹ fi ayọ̀ púpọ̀ gbà á nínú Olúwa; kí ẹ sì máa bu ọlá fún irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀.
ki yuwo Abafaraditu mor Teluwe ki for nerek gwam. kom ne dur nob na co.
30 Nítorí iṣẹ́ Kristi ni ó ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú, tí ó sì fi ẹ̀mí ara rẹ̀ wéwu, láti mu àìtó iṣẹ́ ìsìn yín sí mi kún.
kin ker nangen kiristi ca dadom ca bwiyetiye, con ciya leka dume cek naci mamen nangen do wuro no kom ka matiye.