< Numbers 6 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
Sǝn Israillarƣa eytⱪin: «Mǝyli ǝr yaki ayal bolsun, «Ɵzümni Pǝrwǝrdigarƣa atap, nazariylardin bolimǝn» degǝn alaⱨidǝ bir ⱪǝsǝmni iqkǝn bolsa,
3 irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
undaⱪta u ɵzini ⱨaraⱪ-xarabtin ayrip pǝrⱨiz tutsun; ⱨaraⱪ-xarab bilǝn ixlǝngǝn sirkinimu iqmisun yaki ⱨǝrⱪandaⱪ üzüm xǝrbitini iqmisun wǝ ⱨɵl-ⱪuruⱪ üzümlǝrnimu yemisun.
4 Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
Ɵzini Pǝrwǝrdigarƣa atiƣan barliⱪ künlǝrdǝ, üzüm telidin qiⱪⱪan ⱨǝrⱪandaⱪ nǝrsini, mǝyli üzüm uruⱪi bolsun, posti bolsun, ularni yeyixkǝ bolmaydu.
5 “‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
Ɵzümni Pǝrwǝrdigarƣa atidim dǝp ⱪǝsǝm ⱪilƣan künliridǝ, ularning bexiƣa ustira tǝgküzüxkǝ bolmaydu; ɵzini Pǝrwǝrdigarƣa atiƣan künlǝr ɵtüp bolmiƣuqǝ, u muⱪǝddǝs boluxi kerǝk; ular qaqlirini uzun ⱪoyuxi kerǝk.
6 “‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
U ⱪǝsǝm iqkǝn barliⱪ künliridǝ ⱨeqⱪandaⱪ ɵlüklǝrgǝ yeⱪinlixixⱪa bolmaydu.
7 Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
Uning ɵz atisi, anisi, ⱪerindixi yaki ⱨǝdǝ-singilliri ɵlüp ⱪalƣan bolsa, ularni dǝp ɵzini napak ⱪilmasliⱪi kerǝk; qünki bexida Pǝrwǝrdigarƣila has bolimǝn dǝp bǝrgǝn wǝdisining bǝlgisi bolidu.
8 Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Ɵzini Hudaƣa atiwǝtkǝn barliⱪ künlǝrdǝ u Pǝrwǝrdigar aldida muⱪǝddǝs bolup tursun.
9 “‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
Mubada bir kixi uning yenida tuyuⱪsiz ɵlüp ⱪelip, ɵzini Pǝrwǝrdigarƣa atiƣanliⱪning bǝlgisi bolƣan bexi bulƣanƣan bolsa, u ɵzini paklax küni wǝ keyinki yǝttinqi künimu qeqini aldursun.
10 Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Sǝkkizinqi küni u ikki pahtǝkni yaki ikki baqkini elip jamaǝt qedirining dǝrwazisi aldida kaⱨinƣa tapxursun.
11 Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
Kaⱨin birini gunaⱨ ⱪurbanliⱪi, yǝnǝ birini kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ süpitidǝ sunup, ɵlük sǝwǝbidin napak bolup ⱪalƣan gunaⱨini tilǝp kafarǝt ⱪilsun; nazariy xu künning ɵzidǝ ɵz bexini ⱪaytidin muⱪǝddǝs-pak ⱪilsun,
12 Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
u ɵzini Pǝrwǝrdigarƣa atiƣan künlirini yengiwaxtin baxlisun, xuning bilǝn bir yaxliⱪ bir ǝrkǝk ⱪozini itaǝtsizlik ⱪurbanliⱪi ⱪilip sunsun; ilgiriki künliri bolsa inawǝtsiz ⱨesablansun; qünki uning ɵzini [Pǝrwǝrdigarƣa] atiƣan ⱨaliti bulƣanƣan.
13 “‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Nazariylardin biri ɵzini [Pǝrwǝrdigarƣila] atiƣan künlǝr toxⱪan künidǝ u toƣruluⱪ ⱪanun-bǝlgilimǝ mundaⱪ: — Kixilǝr uni jamaǝt qedirining dǝrwazisi aldiƣa ǝkǝlsun;
14 Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
u ɵzi Pǝrwǝrdigarƣa sunulidiƣan kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ üqün bir yaxliⱪ bejirim ǝrkǝk ⱪozini, gunaⱨ ⱪurbanliⱪi üqün bir yaxliⱪ qixi bejirim bir ⱪozini, inaⱪliⱪ ⱪurbanliⱪi üqün bejirim bir ⱪoxⱪarni kǝltürsun,
15 pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
xundaⱪla bir sewǝt petir nan, zǝytun meyi ilǝxtürülgǝn esil undin pixurulƣan toⱪaqlar ⱨǝmdǝ zǝytun meyi sürülüp mǝsiⱨlǝngǝn petir ⱨǝmǝk nanlar wǝ xu ⱪurbanliⱪlarning ⱪoxumqǝ axliⱪ ⱨǝdiyǝliri wǝ xarab ⱨǝdiyǝlirini kǝltürsun.
16 “‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
Kaⱨin bularni Pǝrwǝrdigarning ⱨuzuriƣa kǝltürüp, Nazariyning xu gunaⱨ ⱪurbanliⱪi bilǝn kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪini sunsun;
17 Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
u Pǝrwǝrdigarƣa atalƣan inaⱪliⱪ ⱪurbanliⱪi süpitidǝ ⱪoxⱪarni sunsun, uningƣa ⱪoxup bir sewǝt petir nanni sunsun; kaⱨin xular bilǝn tǝng Nazariy ⱪoxup tǝⱪdim ⱪilƣan axliⱪ ⱨǝdiyǝ bilǝn xarab ⱨǝdiyǝni kǝltürüp sunsun.
18 “‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
Nazariy jamaǝt qedirining dǝrwazisi aldida ɵzini Pǝrwǝrdigarƣa atiƣanliⱪiƣa bǝlgǝ ⱪilip ⱪoyuwǝtkǝn qeqini qüxürüp, qeqini elip inaⱪliⱪ ⱪurbanliⱪi astidiki otⱪa ⱪoysun.
19 “‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
Nazariy xu tǝriⱪidǝ ɵzini Pǝrwǝrdigarƣila atiƣanliⱪ qeqini qüxürüp bolƣandin keyin, kaⱨin ⱪaynap pixirilƣan ⱪoxⱪarning bir aldi ⱪolini ⱨǝm sewǝttin bir petir nan bilǝn bir petir ⱨǝmǝk nanni elip kelip Nazariyning ⱪoliƣa tutⱪuzsun.
20 Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
Kaⱨin bularni Pǝrwǝrdigarning aldida pulanglatma ⱪurbanliⱪ süpitidǝ ɵrüsun; bular pulanglatma ⱪurbanliⱪ süpitidǝ sunƣan tɵx bilǝn kɵtürmǝ ⱨǝdiyǝ ⱪilinƣan aldi ⱪol bilǝn ⱪoxulup, muⱪǝddǝs dǝp ⱨesablinip kaⱨinƣa berilsun; andin keyin Nazariy xarab iqsǝ bolidu.
21 “‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
Xular bolsa ⱪǝsǝm iqkǝn Nazariy toƣrisida, ɵzini Pǝrwǝrdigarƣa ataxta sunux zɵrür bolƣan ⱪurbanliⱪ-ⱨǝdiyǝlǝr toƣrisida bekitilgǝn ⱪanun-bǝlgilimidur; xuningdǝk uning ⱪoli nemigǝ yǝtsǝ xuni sunsimu bolidu; u iqkǝn ⱪǝsimi boyiqǝ, yǝni ɵzini Hudaƣa atax wǝdisi toƣruluⱪ xu nizam-bǝlgilimǝ boyiqǝ ⱨǝmmǝ ixni ada ⱪilsun; wǝdisigǝ ǝmǝl ⱪilsun.
22 Olúwa sọ fún Mose pé,
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
23 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
Sǝn Ⱨarun bilǝn uning oƣulliriƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ degin: — Silǝr Israillarƣa mundaⱪ bǝht-bǝrikǝt tilǝnglar: —
24 “‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
«Pǝrwǝrdigar silǝrgǝ bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilƣay, silǝrni Ɵz panaⱨida saⱪliƣay;
25 Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
Pǝrwǝrdigar yüzini silǝrning üstünglǝrdǝ yorutup, silǝrgǝ xapaǝt ⱪilƣay;
26 Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
Pǝrwǝrdigar yüzini üstünglarƣa ⱪaritip kɵtürüp, silǝrgǝ hatirjǝmlik bǝrgǝy!» — dǝp tilǝnglar.
27 “Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”
Ular xundaⱪ ⱪilip namimni Israillarning üstigǝ ⱪonduridu wǝ Mǝn ularƣa bǝht-bǝrikǝt ata ⱪilimǝn.

< Numbers 6 >