< Numbers 5 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip: —
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
Sǝn Israillarƣa ǝmr ⱪilip: «Silǝr pisǝ-mahaw kesili bilǝn aⱪma kesiligǝ giriptar bolƣanlarni, xundaⱪla ɵlükkǝ tegixi bilǝn napak bolup ⱪalƣan ⱨǝmmisini ǝr-ayal demǝy bargaⱨtin qiⱪiriwetinglar. Bargaⱨlarni bulƣiwǝtmǝsliki üqün ularni bargaⱨtin qiⱪiriwetinglar; qünki Mǝn bargaⱨ otturisida makan ⱪildim» — degin, — dedi.
3 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
4 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Israillar xundaⱪ ⱪilip ularni bargaⱨtin qiⱪiriwǝtti; Pǝrwǝrdigar Musaƣa ⱪandaⱪ ǝmr ⱪilƣan bolsa, Israillar xundaⱪ ⱪildi.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
6 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
Sǝn Israillarƣa eytⱪin: — Mǝyli ǝr yaki ayal bolsun, ǝgǝr u insanlarning Pǝrwǝrdigarƣa wapasizliⱪ ⱪilidiƣan ⱨǝrⱪandaⱪ gunaⱨliridin birini sadir ⱪilip, xuning bilǝn gunaⱨkar dǝp bekitilsǝ,
7 Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
undaⱪta u ɵzi ɵtküzgǝn gunaⱨiƣa iⱪrar ⱪilip, itaǝtsizliki kǝltürüp qiⱪarƣan, ziyanlanƣuqining ziyinini toluⱪ tɵlǝp berixi kerǝk wǝ uning sirtida u kixigǝ yǝnǝ bǝxtin bir ülüxni ⱪoxup tɵlǝp bǝrsun.
8 Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
Ziyanlanƣuqining mubada itaǝtsizlik kǝltürüp qiⱪarƣan ziyanƣa berilgǝn tɵlǝm pulini alƣudǝk tuƣⱪini bolmisa, tɵlǝm puli gunaⱨkar bolƣan kixining kafaritigǝ sunulidiƣan ⱪoxⱪarƣa ⱪoxulup, Pǝrwǝrdigarƣa atilip, kaⱨinƣa berilsun.
9 Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
Xuningdǝk Israillarning Hudaƣa atiƣan barliⱪ muⱪǝddǝs ⱨǝdiyǝliri, yǝni kaⱨinƣa kǝltürgǝn nǝrsilǝrdin barliⱪ «kɵtürmǝ ⱪurbanliⱪ-ⱨǝdiyǝ»lǝr kaⱨinƣa ⱨesab bolsun.
10 Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
Ⱨǝrkim Hudaƣa atiƣan ⱨǝdiyǝlǝr muⱪǝddǝs dǝp ⱨesablansun, xundaⱪla kaⱨinning bolsun; kixilǝr kaⱨinƣa nemǝ ⱨǝdiyǝ ⱪilsa, uning ⱨǝmmisi kaⱨinning bolsun.
11 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
Pǝrwǝrdigar Musaƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi: —
12 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
Sǝn Israillarƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ degin: — Əgǝr birsining hotuni ɵz eridin yüz ɵrügǝn, sadaⱪǝtsizlik ⱪilƣan bolsa,
13 nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
— demǝk, baxⱪa birsi bilǝn yeⱪinlaxⱪan, xundaⱪla uning bulƣanƣanliⱪi erining kɵzliridin yoxurun bolƣan bolsa, ⱨeq guwaⱨqi bolmiƣan ⱨǝm gunaⱨ ⱪilƣan qeƣida tutulupmu ⱪalmiƣan bolsa,
14 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
xundaⱪ ǝⱨwalda, eri ɵz hotunidin guman ⱪilip künlisǝ, hotuni rastla zina ⱪilip bulƣanƣan bolsa (yaki ɵz hotuniƣa guman ⱪilip künlisimu, hotuni zina ⱪilmiƣan wǝ bulƣanmiƣan bolsa)
15 nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
ǝⱨwalini ispatlax üqün bu adǝm hotunini kaⱨinning yeniƣa ǝkǝlsun ⱨǝm hotuni üqün zɵrür axliⱪ ⱨǝdiyǝsi, yǝni arpa undin ondin bir ǝfaⱨni alƣaq kǝlsun; xu ⱨǝdiyǝning üstigǝ u ⱨeq zǝytun meyi ⱪuymisun yaki ⱨeq mǝstiki ⱪoxup ⱪoymisun; qünki bu kündaxliⱪ ⱨǝdiyǝsi, ǝslǝtmǝ axliⱪ ⱨǝdiyǝsi bolup, ularning ⱪǝbiⱨlikigǝ bolƣan ǝslǝtmidur.
16 “‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
Kaⱨin u hotunni aldiƣa kǝltürüp, Pǝrwǝrdigarning ⱨuzurida turƣuzsun.
17 Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
Kaⱨin komzǝkkǝ muⱪǝddǝs sudin ⱪuyup, ibadǝt qedirining yǝr topisidin bir qimdim elip suƣa qeqip ⱪoysun.
18 Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
Kaⱨin u hotunni Pǝrwǝrdigarning ⱨuzurida turƣuzup, bexini eqip, ǝslǝtmǝ axliⱪ ⱨǝdiyǝsi, yǝni kündaxliⱪ ⱨǝdiyǝsini uning ⱪoliƣa tutⱪuzsun, andin kaⱨin ⱪoliƣa ⱪarƣix kǝltürgüqi ǝlǝm süyini alsun.
19 Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
Kaⱨin u hotunƣa ⱪǝsǝm iqküzüp, uningƣa «Dǝrwǝⱪǝ sǝn ⱨeqⱪandaⱪ adǝm bilǝn billǝ yatmiƣan, eringning ornida baxⱪa birsi bilǝn billǝ boluxⱪa ezip buzuⱪluⱪ ⱪilmiƣan bolsang, undaⱪta sǝn bu ⱪarƣix kǝltürgüqi ǝlǝm süyidin halas bolƣaysǝn.
20 Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
Lekin sǝn eringning ornida baxⱪa birsigǝ yeⱪinlixip ɵzüngni bulƣiƣan bolsang, eringdin baxⱪa bir ǝr sǝn bilǝn billǝ yatⱪan bolsa, —» desun;
21 nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
andin kaⱨin u hotunƣa ⱪarƣix ⱪǝsimini iqküzgǝndin keyin, yǝnǝ uningƣa: «— Pǝrwǝrdigar yotangni yiglitip, ⱪorsiⱪingni ixxitiwǝtsun, xuningdǝk Pǝrwǝrdigar seni ɵz hǝlⱪing iqidǝ ⱪarƣix wǝ ⱪǝsǝm iqix dǝstikigǝ aylandursun; bu ⱪarƣix süyi iq-ⱪarningƣa kirip, ⱪorsiⱪingni ixxitiwǝtsun, yotangni yigilitiwǝtsun» degǝndǝ, u hotun: «Amin, amin» desun.
22 Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
23 “‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
Xuningdǝk kaⱨin bu ⱪarƣix sɵzlirini dǝptǝrgǝ pütüp ⱪoysun, xundaⱪla yazƣan sɵzlǝrni ǝlǝm süyigǝ qilisun,
24 Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
andin u hotunƣa bu ⱪarƣix kǝltürgüqi ǝlǝm süyini iqküzsun, bu ⱪarƣix kǝltürgüqi su uning iqigǝ kirixi bilǝnla uningƣa azab-ǝlǝm bolidu.
25 Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
Kaⱨin u hotunning ⱪolidin kündaxliⱪ axliⱪ ⱨǝdiyǝsini elip, uni Pǝrwǝrdigarning ⱨuzurida pulanglitip bolƣandin keyin, ⱪurbangaⱨⱪa elip kǝlsun.
26 Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
Kaⱨin ⱨǝdiyǝdin bir siⱪim un elip, hatirǝ ⱨesabida ⱪurbangaⱨⱪa ⱪoyup kɵydürsun; andin u hotunƣa bu suni iqküzsun.
27 Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Kaⱨin ǝmdi u hotunƣa suni iqküzgǝndin keyin, ǝgǝr u ⱨǝⱪiⱪiy bulƣanƣan bolup, ɵz erigǝ sadaⱪǝtsizlik ⱪilƣan bolsa, qoⱪum xundaⱪ boliduki, bu ⱪarƣix süyi uning iqigǝ kirgǝndin keyin uningƣa azab-ǝlǝm kǝltüridu; uning ⱪorsiⱪi ixxip, yotisi yigilǝp ketidu; xuning bilǝn u hotun ɵz hǝlⱪi iqidǝ ⱪarƣixⱪa ketidu.
28 Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
Lekin ǝgǝr u hotun bulƣanmiƣan pak bolsa, xu ixtin halas bolidu wǝ ǝksiqǝ ⱨamilidar bolup pǝrzǝntlik bolidu.
29 “‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
Mana bu kündaxliⱪ toƣrisidiki ⱪanundur; hotun ɵz erining ornida baxⱪa birsi bilǝn billǝ boluxi bilǝn ezip bulƣanƣan bolsa
30 tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
wǝ yaki birsi hotunidin guman ⱪilip künlisǝ, undaⱪta u hotunini Pǝrwǝrdigarning aldida turƣuzsun, kaⱨin uningƣa xu ⱪanun boyiqǝ ⱨǝmmini ijra ⱪilsun.
31 Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”
Ənǝ xundaⱪ ⱪilƣanda, ǝr gunaⱨtin halas bolup, hotun ɵz gunaⱨini kɵtiridu.

< Numbers 5 >