< Numbers 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Potem PAN powiedział do Mojżesza:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
Rozkaż synom Izraela i powiedz im: Gdy wejdziecie do ziemi Kanaan, to jest ziemia, która wam przypadnie jako dziedzictwo, ziemia Kanaan w swoich granicach;
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
Wasza południowa granica będzie od pustyni Syn wzdłuż granic Edomu, a granica południowa pobiegnie od brzegu Morza Słonego, od wschodu.
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
Granica ta skręci od południa ku Maale-Akrabbim i pobiegnie aż do Syn, i dojdzie od południa do Kadesz-Barnea. Stamtąd pobiegnie do Chasar-Addar i przejdzie aż do Asmon.
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
A ta granica skręci od Asmon aż do rzeki Egiptu, a skończy się przy morzu.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
Jako zachodnią granicę będziecie mieli Morze Wielkie – ono będzie waszą zachodnią granicą.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
A to będzie wasza północna granica: od Morza Wielkiego wymierzycie sobie do góry Hor.
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
Potem od góry Hor wymierzycie granicę aż do wejścia do Hemat; a krańce tej granicy sięgną do Sedada.
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
Następnie granica ta pobiegnie aż do Zifronu, a skończy się w Chasar-Enan. To będzie wasza północna granica.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
A wschodnią granicę wymierzycie od Chasar-Enan do Szefam.
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
Granica ta pobiegnie od Szefam aż do Ribla, od wschodu Ain; i ta granica zejdzie w dół, i dosięgnie brzegu morza Kinneret od wschodu.
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
Następnie ta granica zejdzie ku Jordanowi, a zakończy się przy Morzu Słonym. To będzie wasza ziemia ze swymi granicami wokoło.
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
Wtedy Mojżesz rozkazał synom Izraela: To jest ziemia, którą odziedziczycie przez losowanie, którą PAN rozkazał dać dziewięciu i pół pokoleniu.
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
Bo pokolenie synów Rubena według domów swych ojców i pokolenie synów Gada według domów swych ojców już otrzymały swoje dziedzictwo i połowa pokolenia Manassesa już otrzymała swoje dziedzictwo.
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
Te dwa i pół pokolenia otrzymały swoje dziedzictwo po tej stronie Jordanu, naprzeciw Jerycha, na wschodzie.
16 Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
Oto imiona mężczyzn, którzy rozdzielą wam ziemię: kapłan Eleazar i Jozue, syn Nuna.
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
Weźmiecie też po jednym naczelniku z każdego pokolenia do rozdzielenia ziemi w dziedzictwo.
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
A oto imiona tych mężczyzn: z pokolenia Judy – Kaleb, syn Jefunnego.
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
Z pokolenia synów Symeona – Samuel, syn Ammihuda.
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
Z pokolenia Beniamina – Eliad, syn Kislona.
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
Z pokolenia synów Dana – naczelnik Bukki, syn Jogliego.
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
Z synów Józefa, z pokolenia synów Manassesa – naczelnik Channiel, syn Efoda;
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
A z pokolenia synów Efraima – naczelnik Kemuel, syn Sziftana.
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
Z pokolenia Zebulona – naczelnik Elisafan, syn Parnacha.
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
Z pokolenia synów Issachara – naczelnik Paltiel, syn Azzana.
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
Z pokolenia synów Aszera – naczelnik Achihud, syn Szelomiego.
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
A z pokolenia synów Neftalego – naczelnik Pedahel, syn Ammihuda.
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
To są ci, którym PAN rozkazał rozdzielić dziedzictwo synom Izraela w ziemi Kanaan.

< Numbers 34 >