< Numbers 31 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
2 “Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
Pomścij krzywdy synów Izraela na Midianitach. Potem zostaniesz przyłączony do swego ludu.
3 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
Mojżesz powiedział więc do ludu: Przygotujcie spośród siebie mężczyzn do bitwy, aby wyruszyli przeciw Midianitom i dokonali na nich zemsty PANA.
4 Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
Wyślecie na wojnę po tysiącu z każdego pokolenia, ze wszystkich pokoleń Izraela.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
I wyznaczono z tysięcy Izraela po tysiącu [z każdego] pokolenia, dwanaście tysięcy gotowych do walki.
6 Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
I Mojżesz wysłał ich na wojnę po tysiącu [z każdego] pokolenia; [posłał też] z nimi Pinchasa, syna kapłana Eleazara, na wojnę, a w jego ręku [były] święte sprzęty i trąby sygnałowe.
7 Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
Wtedy walczyli z Midianitami, jak PAN rozkazał Mojżeszowi, i pozabijali wszystkich mężczyzn.
8 Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
Oprócz innych zabitych, zabili też królów Midianu: Ewiego, Rekema, Sura, Chura i Rebę – pięciu królów Midianu. Zabili też mieczem Balaama, syna Beora.
9 Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
Synowie Izraela wzięli do niewoli kobiety Midianu i ich dzieci; zabrali też całe ich bydło i trzody, i cały ich majątek;
10 Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
Spalili też ogniem wszystkie ich miasta, w których mieszkali, oraz wszystkie ich zamki;
11 Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
I zabrali cały łup oraz całą zdobycz zarówno z ludzi, jak i ze zwierząt;
12 Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
I przyprowadzili więźniów, zdobycz i łup do Mojżesza, do kapłana Eleazara i do zgromadzenia synów Izraela, do obozu na równinach Moabu, które są nad Jordanem, [naprzeciw] Jerycha.
13 Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
A Mojżesz, kapłan Eleazar i wszyscy naczelnicy zgromadzenia wyszli im naprzeciw poza obóz.
14 Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
I Mojżesz bardzo się rozgniewał na dowódców wojska, tysiączników i setników, którzy wrócili z walki.
15 Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
I mówił do nich Mojżesz: Czy zostawiliście przy życiu wszystkie kobiety?
16 Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
Oto one za radą Balaama spowodowały, że synowie Izraela dopuścili się przewinienia przeciwko PANU w związku z Peorem, a to sprowadziło plagę na zgromadzenie PANA.
17 Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
Zabijcie więc teraz wszystkich chłopców spośród dzieci, zabijcie też każdą kobietę, która obcowała z mężczyzną;
18 ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
Lecz wszystkie dziewczyny, które nie obcowały z mężczyzną, zostawcie przy życiu dla siebie.
19 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
A wy sami zostańcie przez siedem dni poza obozem. Każdy, kto zabił człowieka, i każdy, kto dotknął zabitego, niech się oczyści trzeciego i siódmego dnia, wy i wasi jeńcy.
20 Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
Oczyśćcie również każdą szatę, wszelkie przedmioty skórzane i wszystko, co wykonano z koziej sierści, a także wszelkie drewniane przedmioty.
21 Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
Potem kapłan Eleazar powiedział do wojowników, którzy wyruszyli na wojnę: Taka jest ustawa prawa, którą PAN nadał Mojżeszowi:
22 Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
Tylko złoto, srebro, miedź, żelazo, cynę i ołów;
23 Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
Wszystko, co może znieść ogień, przeprowadzicie przez ogień i będzie czyste; jednak [najpierw] będzie oczyszczone wodą oczyszczenia. Wszystko zaś, co nie może znieść ognia, oczyścicie wodą.
24 Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
Siódmego dnia wypierzecie też swoje szaty i będziecie czyści, a potem wejdziecie do obozu.
25 Olúwa sọ fún Mose pé,
Następnie PAN powiedział do Mojżesza:
26 “Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
Razem z kapłanem Eleazarem i głowami spośród ojców zgromadzenia policz całą zdobycz uprowadzoną w ludziach i zwierzętach;
27 Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
I podziel zdobycz na dwie części: pomiędzy tych, którzy wyruszyli na wojnę, i pomiędzy całe zgromadzenie.
28 Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
Od wojowników, którzy wyruszyli na wojnę, pobierz też daninę dla PANA, po jednym na pięćset, [tak] z ludzi, [jak] i wołów, osłów i owiec;
29 Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
Weź to z ich połowy i oddaj kapłanowi Eleazarowi na ofiarę wzniesienia dla PANA.
30 Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
A z połowy synów Izraela weź po jednym z pięćdziesięciu z ludzi, wołów, osłów, owiec, [słowem] ze wszystkich zwierząt, i oddaj to Lewitom, którzy pełnią straż przy przybytku PANA.
31 Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
I Mojżesz, i kapłan Eleazar uczynili tak, jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
32 Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
A zdobycz z pozostałego łupu, który zdobyli wojownicy, wynosiła sześćset siedemdziesiąt pięć tysięcy owiec;
33 Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
Siedemdziesiąt dwa tysiące wołów;
34 ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
Sześćdziesiąt jeden tysięcy osłów;
35 pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
I trzydzieści dwa tysiące kobiet, które nie obcowały z mężczyzną.
36 Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
Połowa przypadająca w udziale tym, którzy wyruszyli na wojnę, wynosiła trzysta trzydzieści siedem tysięcy pięćset owiec.
37 Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
Danina dla PANA z tych owiec wynosiła sześćset siedemdziesiąt pięć [sztuk].
38 ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
Wołów [było] trzydzieści sześć tysięcy, a z tego danina dla PANA – siedemdziesiąt dwie;
39 kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
Osłów [było] trzydzieści tysięcy pięćset, a z tego danina dla PANA – sześćdziesiąt jeden.
40 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
Ludzi [było] szesnaście tysięcy, a z tego danina dla PANA – trzydzieści dwie osoby.
41 Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
I Mojżesz oddał kapłanowi Eleazarowi daninę na ofiarę wzniesienia dla PANA, tak jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
42 Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
A z połowy należącej do synów Izraela, którą Mojżesz oddzielił od tych, którzy wyruszyli na wojnę;
43 Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
(Połowa [należąca] do zgromadzenia wynosiła trzysta trzydzieści siedem tysięcy pięćset owiec;
44 pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
Trzydzieści sześć tysięcy wołów;
45 tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Trzydzieści tysięcy pięćset osłów;
46 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
I szesnaście tysięcy osób).
47 Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
Z tej połowy [należącej] do synów Izraela Mojżesz wziął po jednym na pięćdziesiąt z ludzi i zwierząt, i dał to Lewitom pełniącym straż przy przybytku PANA, tak jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
48 Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
Wtedy przyszli do Mojżesza dowódcy wojska, tysiącznicy i setnicy.
49 Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
I powiedzieli do niego: My, twoi słudzy, policzyliśmy wojowników, którzy [byli] pod naszym dowództwem, i nie brakuje z nas ani jednego.
50 Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
Dlatego przynieśliśmy na ofiarę dla PANA [to], co każdy zdobył: złote przedmioty, łańcuszki, bransolety, pierścienie, kolczyki i naszyjniki, by dokonać przebłagania za nasze dusze przed PANEM.
51 Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
Mojżesz i kapłan Eleazar przyjęli więc od nich to złoto, wszystkie wykonane przedmioty.
52 Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
A całego złota tej ofiary, którą oddali PANU, od tysiączników i setników, było szesnaście tysięcy siedemset pięćdziesiąt syklów.
53 Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
Wojownicy bowiem zatrzymali łup, każdy dla siebie.
54 Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.
Mojżesz i kapłan Eleazar przyjęli to złoto od tysiączników i setników i zanieśli do Namiotu Zgromadzenia jako pamiątkę synów Izraela przed PANEM.

< Numbers 31 >