< Numbers 30 >

1 Mose sì sọ fún olórí àwọn ẹ̀yà ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ,
Potem Mojżesz powiedział do naczelników pokoleń pośród synów Izraela: Oto co PAN rozkazał.
2 nígbà tí ọkùnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ ní ìdè kí òun má bà ba ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sọ.
Jeśli mężczyzna złoży PANU ślub lub przysięgę i zwiąże swoją duszę zobowiązaniem, to nie złamie swego słowa; wypełni wszystko według tego, co wyszło z jego ust.
3 “Nígbà tí ọmọbìnrin kan bá sì wà ní ilé baba rẹ̀ tó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀
Jeśli kobieta złoży PANU ślub i zwiąże się zobowiązaniem w domu swego ojca, w swojej młodości;
4 tí baba rẹ̀ bá sì gbọ́ ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí ìdè rẹ̀ tí kò sì sọ nǹkan kan sí i, kí gbogbo ẹ̀jẹ́ rẹ̀ kí ó dúró àti gbogbo ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ yóò sì dúró.
A jej ojciec usłyszy ślub i zobowiązanie, którym związała swoją duszę, a jej ojciec będzie milczał o tym, wtedy wszystkie jej śluby będą ważne i każde zobowiązanie, którym związała swą duszę, będzie ważne.
5 Ṣùgbọ́n tí baba rẹ̀ bá kọ̀ fun un ní ọjọ́ tí ó gbọ́, kò sí ọ̀kan nínú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí nínú ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tí yóò dúró; Olúwa yóò sì tú u sílẹ̀ nítorí baba rẹ̀ kọ̀ fún un.
Lecz jeśli jej ojciec sprzeciwi się jej w dniu, kiedy usłyszy o wszystkich jej ślubach i zobowiązaniach, którymi związała swoją duszę, wtedy nie będą ważne; PAN przebaczy jej, gdyż jej ojciec sprzeciwił się temu.
6 “Tí ó bá sì ní ọkọ lẹ́yìn ìgbà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí lẹ́yìn ìgbà tí ó sọ ọ̀rọ̀ kan láti ẹnu rẹ̀ jáde nínú èyí tí ó fi de ara rẹ̀ ní ìdè,
Ale jeśli mając męża, złożyła ślub lub wypowiedziała swymi ustami coś, czym związała swoją duszę;
7 tí ọkọ rẹ̀ sì gbọ́ nípa èyí ṣùgbọ́n tí kò sọ nǹkan kan, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tó dúró.
A jej mąż to usłyszał i milczał o tym w dniu, gdy to usłyszał, to jej śluby będą ważne i jej zobowiązania, którymi związała swoją duszę, będą ważne.
8 Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá kọ̀ nígbà tí ó gbọ́, ǹjẹ́ òun yóò mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ́ àti ohun tí ó ti ti ẹnu rẹ̀ jáde, èyí tí ó fi de ara rẹ̀ dasán, Olúwa yóò sì dáríjì í.
Lecz jeśli w dniu, gdy jej mąż usłyszał o tym, sprzeciwił się temu, to unieważnia jej ślub, który złożyła, i to, co wypowiedziała swymi ustami, czym związała swoją duszę; a PAN jej przebaczy.
9 “Ṣùgbọ́n ẹ̀jẹ́ kí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè kí ìdè tí opó tàbí obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ bá ṣe yóò wà lórí rẹ̀.
Ale każdy ślub wdowy i rozwiedzionej, którym związały swoją duszę, będzie ważny.
10 “Bí obìnrin tí ó ń gbé pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí de ara rẹ̀ ní ìdè lábẹ́ ìbúra,
Lecz jeśli w domu swego męża złożyła ślub lub związała swoją duszę zobowiązaniem przysięgi;
11 tí ọkọ rẹ̀ bá sì gbọ́, ṣùgbọ́n tí kò sọ̀rọ̀, tí kò sì kọ̀, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ rẹ̀ yóò dúró.
A jej mąż usłyszał to i milczał o tym, i nie sprzeciwił się temu, wtedy wszystkie jej śluby będą ważne i każdy obowiązek, którym zobowiązała swoją duszę, będzie ważny.
12 Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá sọ wọ́n dasán, nígbà tí ó gbọ́, nígbà náà kò sí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde tí yóò dúró, ọkọ rẹ̀ ti sọ wọ́n dasán, Olúwa yóò tú u sílẹ̀.
Ale jeśli jej mąż sprzeciwił się temu w dniu, kiedy to usłyszał, to wszelki ślub i zobowiązanie, jakie padły z jej ust, będą nieważne; jej mąż je unieważnił; a PAN jej przebaczy.
13 Ọkọ rẹ̀ lè ṣe ìwádìí tàbí sọ ọ́ dasán ẹ̀jẹ́ tàbí ìbúra ìdè tí ó ti ṣe láti fi de ara rẹ̀.
Wszelki ślub i wszelką przysięgę zobowiązania na trapienie duszy może jej mąż potwierdzić lub może unieważnić.
14 Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó ṣe ìwádìí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà ṣe ìwádìí lórí rẹ̀ láìsọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀.
A jeśli jej mąż będzie milczał dzień po dniu, to potwierdza wszystkie jej śluby i wszystkie jej zobowiązania, które ją wiążą. Potwierdza je, ponieważ milczał o tym w dniu, kiedy [je] usłyszał;
15 Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yìn tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”
Lecz jeśli je usłyszał i dopiero później unieważni, to poniesie jej nieprawość.
16 Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mose nípa ìbátan láàrín ọkùnrin àti obìnrin àti láàrín baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.
To są ustawy, które PAN przykazał Mojżeszowi, między mężem a jego żoną, między ojcem a jego córką w jej młodości, [póki jest] w domu swego ojca.

< Numbers 30 >