< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Nämät ovat Israelin lasten matkustukset, kuin he läksivät Egyptin maalta, joukkoinsa jälkeen, Moseksen ja Aaronin kautta.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Ja Moses kirjoitti heidän matkustuksensa, niinkuin he matkustivat Herran käskyn jälkeen. Ja nämät ovat heidän matkustuksensa heidän lähdentönsä jälkeen:
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
Ja he matkustivat Ramesesta viidentenätoistakymmenentenä päivänä ensimäisenä kuukautena: toisena päivänä pääsiäisestä, läksivät Israelin lapset ulos korkian käden kautta, kaikkein Egyptiläisten nähden.
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
Ja Egyptiläiset hautasivat kaikki esikoisensa, jotka Herra heidän seassansa lyönyt oli, ja Herra oli myös antanut tuomion käydä heidän jumalainsa ylitse.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Koska Israelin lapset olivat vaeltaneet Ramesesta, niin he sioittivat itsensä Sukkotiin.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Ja matkustivat Sukkotista, ja sioittivat itsensä Etamiin, joka on korven äärellä.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Ja he matkustivat Etamista ja palasivat PiiHahirotiin, joka on BaalZephoniin päin, ja sioittivat itsensä Migdolin kohdalle.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Ja he matkustivat Hahirotin editse ja kävivät keskeltä merta korpeen, ja matkustivat kolme päiväkuntaa Etamin korvessa, ja sioittivat itsensä Maraan.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Ja he matkustivat Marasta ja tulivat Elimiin: ja Elimissä oli kaksitoistakymmentä lähdettä, ja seitsemänkymmentä palmupuuta, ja sioittivat itsensä siellä.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Ja he matkustivat Elimistä, ja sioittivat itsensä Punaisen meren tykö.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Ja matkustivat Punaisen meren tyköä, ja sioittivat itsensä Sinin korpeen.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Ja he matkustivat Sinin korvesta, ja sioittivat itsensä Dophkaan.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Ja he matkustivat Dophkasta, ja sioittivat itsensä Alusiin.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Ja he matkustivat Alusista, ja sioittivat itsensä Raphidimiin, ja siinä ei ollut kansalle vettä juoda.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
Ja he matkustivat Raphidimista, ja sioittivat itsensä Sinain korpeen.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Ja he matkustivat Sinain korvesta, ja sioittivat itsensä Himohaudoille.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Ja he matkustivat Himohaudoilta, ja sioittivat itsensä Hatserotiin.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Ja he matkustivat Hatserotista, ja sioittivat itsensä Ritmaan.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Ja he matkustivat Ritmasta, ja sioittivat itsensä Rimmon Paretsiin.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Ja he matkustivat Rimmon Paretsista, ja sioittivat itsensä Libnaan.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Ja he matkustivat Libnasta, ja sioittivat itsensä Rissaan.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Ja he matkustivat Rissasta, ja sioittivat itsensä Kehelaan.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Ja he matkustivat Kehelasta, ja sioittivat itsensä Sapherin vuorelle.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Ja he matkustivat Sapherin vuorelta, ja sioittivat itsensä Haradaan.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Ja he matkustivat Haradasta ja sioittivat itsensä Makhelotiin.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Ja he matkustivat Makhelotista, ja sioittivat itsensä Tahatiin.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Ja he matkustivat Tahatista, ja sioittivat itsensä Taraan.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Ja he matkustivat Tarasta, ja sioittivat itsensä Mitkaan.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Ja he matkustivat Mitkasta, ja sioittivat itsensä Hasmonaan.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Ja he matkustivat Hasmonasta, ja sioittivat itsensä Moserotiin.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Ja he matkustivat Moserotista, ja sioittivat itsensä BeneJaekaniin.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Ja he matkustivat BeneJaekanista, ja sioittivat itsensä Horgidgadiin.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Ja he matkustivat Horgidgadista, ja sioittivat itsensä Jotbataan.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
Ja he matkustivat Jotbatasta, ja sioittivat itsensä Abronaan.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Ja he matkustivat Abronasta, ja sioittivat itsensä Etseongeberiin.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Ja he matkustivat Etseongeberistä, ja sioittivat itsensä Sinin korpeen, se on Kades.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Ja he matkustivat Kadeksesta, ja sioittivat itsensä Horin vuorelle, joka on Edomin maan rajoilla.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
Siinä meni pappi Aaron Horin vuorelle, Herran käskyn jälkeen, ja kuoli siellä neljäntenäkymmenentenä vuotena, sittekuin Israelin lapset olivat lähteneet Egyptin maalta, ensimäisenä päivänä viidennestä kuusta.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Ja Aaron oli sadan ja kolmenkolmattakymmentä vuotinen kuollessansa Horin vuorella.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
Silloin kuuli Arad Kanaanealaisten kuningas, joka asui etelään päin Kanaanin maalla, että Israelin lapset tulleet olivat.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Ja he matkustivat Horin vuorelta, ja sioittivat itsensä Salmonaan.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
Ja he matkustivat Salmonasta, ja sioittivat itsensä Phunoniin.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Ja he matkustivat Phunonista, ja sioittivat itsensä Obotiin.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Ja he matkustivat Obotista, ja sioittivat itsensä Iije Abarimiin, Moabin rajoille.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Ja he matkustivat Iijestä, ja sioittivat itsensä DibonGadiin.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Ja he matkustivat DibonGadista, ja sioittivat itsensä AlmonDiblataimiin.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Ja he matkustivat AlmonDiblataimista, ja sioittivat itsensä Abarimin vuorille Nebon kohdalle.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Ja he matkustivat Abarimin vuorilta, ja sioittivat itsensä Moabin kedoille, Jordanin tykö, Jerihon kohdalle.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Ja he sioittivat itsensä Jordanin tykö hamasta BetJesimotista, niin AbelSittimiin Moabin kedoille.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Ja Herra puhui Mosekselle, Moabin kedoilla, Jordanin tykönä Jerihon kohdalla, sanoen:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Puhu Israelin lapsille, ja sano heille: kuin te olette tulleet Jordanin ylitse Kanaanin maalle,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
Niin teidän pitää kaikki sen maan asuvaiset teidän edestänne ajaman pois, ja kaikki heidän maalauksensa ja valetut kuvansa hukuttaman, ja kaikki heidän korkeutensa hävittämän,
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
Ja niin teidän pitää maan omistaman ja asuman siinä; sillä teille olen minä maan antanut omistaaksenne sen.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
Ja teidän pitää maan jakaman arvalla teidän sukukunnillenne. Joita usiampi on, niille pitää teidän enempi antaman perinnöksensä, ja joita vähempi on, niille vähemmän perinnöksensä; kuin arpa lankee kullekin, niin pitää hänen sen ottaman: teidän isäinne sukukuntain jälkeen pitää teidän perimän.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Mutta jollette maan asuvaisia aja ulos teidän edestänne, niin pitää ne, jotka te heistä jätätte, oleman teille niinkuin orjantappurat silmissänne, ja keihäs kyljessänne; sillä heidän pitää ahdistaman teitä sillä maalla, kussa te asutte.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Niin tapahtuu, että minä teen niin teille, kuin minä aioin heille tehdä.

< Numbers 33 >