< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Nämät ovat ne sanat, mitkä Moses puhui koko Israelille, tällä puolella Jordania korvessa, sillä kedolla Punaisen meren kohdalla, Paranin, ja Tophelin, ja Labanin, ja Hatserotin ja Disahabin vaiheella,
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
Yksitoistakymmentä päiväkuntaa Horebista, sitä tietä Seirin vuoren kautta niin KadesBarneaan asti.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Ja tapahtui neljäntenäkymmenentenä vuonna, ensimäisenä päivänä, ensimäisellä kuukaudella toistakymmentä, että Moses puhui Israelin lapsille kaikki, mitä Herra hänen käski heille puhua.
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Sittekuin hän oli lyönyt Sihonin Amorilaisten kuninkaan, joka Hesbonissa asui, niin myös Ogin, Basanin kuninkaan, joka Astarotissa Edreissä asui,
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Tällä puolella Jordania, Moabin maalla, rupesi Moses selittämään tätä lakia ja sanoi:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
Herra meidän Jumalamme puhui meille Horebissa, sanoen: te olette jo kyllä kauvan olleet tällä vuorella;
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Kääntäkäät teitänne ja menkäät matkaan Amorilaisten vuorelle, ja kaikkein heidän läsnä asuvaistensa tykö, kedoilla, vuorella ja laaksossa, etelämaalle, ja meren satamissa, Kanaanin maalle ja Libanoniin, hamaan suuren Phratin virran tykö.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Katso, minä annoin teille maan, joka on teidän edessänne: menkäät ja omistakaat se maa, niinkuin Herra teidän isillenne Abrahamille, Isaakille ja Jakobille vannoi, antaaksensa sen heille ja heidän siemenellensä heidän jälkeensä.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
Ja minä puhuin teille silloin, sanoen: en minä voi yksinäni kantaa teitä.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Sillä Herra teidän Jumalanne on lisännyt teitä, niin että te tänäpänä olette niin monta, kuin tähdet taivaassa.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Herra teidän isäinne Jumala lisätköön teitä vielä monta tuhatta kertaa enempi, ja siunatkoon teitä, niinkuin hän teille sanonut on.
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Kuinka minä yksinäni voin kantaa senkaltaisen vaivan, kuorman ja riidan teiltä?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Valitkaat teistänne toimelliset ja ymmärtäväiset miehet, jotka teidän suvustanne tunnetut ovat, ja minä asetan heitä teidän päämiehiksenne.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Niin te vastasitte minua, sanoen: se on hyvä asia, josta puhut tehdäkses.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Niin minä otin ylimmäiset teidän suvuistanne, toimmelliset ja tunnetut miehet, ja asetin teille päämiehiksi, tuhannen, sadan, viidenkymmenen ja kymmenen päälle, ja esimiehiksi sukukunnissanne.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
Ja minä käskin tuomareille silloin, sanoen: kuulkaat teiden veljiänne, ja tuomitkaat oikein jokaisen miehen ja hänen veljensä vaiheella, ja hänen muukalaisensa vaiheella.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Ei teidän pidä katsoman kenenkään muotoa tuomiossa, vaan kuulkaat niin pientä, kuin suurtakin: älkäät peljätkö kenenkään muotoa; sillä tuomio on Jumalan: vaan se asia, mikä teille on raskas, antakaat tulla minun eteeni, kuullakseni sitä.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
Ja minä käskin teitä siihen aikaan kaikista, mitä teidän tekemän piti.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Niin me läksimme Horebista, ja vaelsimme kaiken sen suuren ja hirmuisen korven lävitse, jonka te nähneet olette Amorilaisten vuoren tiellä, niinkuin Herra meidän Jumalamme meille käski. Ja tulimme KadesBarneaan.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
Niin sanoin minä teille: te olette tulleet Amorilaisten vuoreen asti, jonka Herra meidän Jumalamme antaa meille.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Katso sitä maata sinun edessäs, jonka Herra sinun Jumalas sinulle antanut on, mene, ja omista se niinkuin Herra sinun isäis Jumala sinulle sanonut on: älä pelkää, älä myös hämmästy.
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Ja te tulitte kaikki minun tyköni, ja sanoitte: lähettäkäämme miehet meidän edellämme vakoomaan maata, ja meille asiaa ilmoittamaan, ja tietä, jota meidän sinne menemän pitää, ja kaupungeita, joihin meidän tuleman pitää.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Ja se asia kelpasi minulle: niin otin minä kaksitoistakymmentä miestä teidän seastanne, jokaisesta sukukunnasta yhden.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Ne menivät matkaansa, ja astuivat vuorelle, ja tulivat Eskolin ojaan asti, ja vakosivat sen.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Ja ottivat maan hedelmästä myötänsä ja toivat meille, ja ilmoittivat meille asian, ja sanoivat: maa on hyvä, jonka Herra meidän Jumalamme meille antaa.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
Mutta ette tahtoneet mennä sinne, vaan olitte vastahakoiset Herran teidän Jumalanne sanalle,
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Ja napisitte majoissanne ja sanoitte: Herra on meille vihainen, ja on tuonut meitä ulos Egyptin maalta, antaaksensa meitä Amorilaisten käsiin, hukutettaa.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Kuhunka me menemme? Meidän veljemme ovat peljättäneet meidän sydämemme, sanoen: se kansa on suurempi ja pitempi meitä, ja ne kaupungit ovat suuret ja varustetut taivaasen asti: olemme myös nähneet siellä Enakin pojat.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Ja minä sanoin teille: älkäät hämmästykö, älkäät myös peljästykö heitä;
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Sillä Herra teidän Jumalanne käy teidän edellänne, ja sotii teidän edestänne, niin kuin hän myös tehnyt on Egyptissä teille teidän silmäinne edessä,
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
Ja korvessa, jossa sinä olet nähnyt, kuinka Herra sinun Jumalas on sinun kantanut, niinkuin mies kantaa poikansa, kaikella sillä tiellä, jota te vaeltaneet olette, siihenasti kuin te tälle paikalle tulitte.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Vaan ette siitä lukua pitäneet, uskoa Herran teidän Jumalanne päälle,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
Joka kävi tiellä teidän edellänne, tiedustamaan leirin paikkaa, yöllä tulessa, osoittaen teille tietä jota te kävitte, ja päivällä pilvessä.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Koska Herra kuuli teidän huutonne, vihastui hän ja vannoi, sanoen:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
Ei yksikään tästä pahasta sukukunnasta pidä näkemän sitä hyvää maata, jonka minä olen vannonut, antaakseni teidän isillänne,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
Paitsi Kalebia Jephunnen poikaa, hän näkee sen, hänelle minä annan sen maan, jonka päälle hän astunut on, ja myös hänen lapsillensa, että hän uskollisesti seurasi Herraa.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Ja Herra vihastui myös minulle teidän tähtenne, et sinäkään sinne tule;
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Vaan Josua Nunin poika, sinun palvelias, hän tulee sinne: vahvista häntä; sillä hänen pitää asettaman Israelin perimykseensä.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Ja teidän lapsenne, jotka te sanoitte saaliiksi tulevan, ja teidän poikanne, jotka ei tänäpänä tiedä hyvää eli pahaa, he tulevat sinne, ja minä annan sen heille, ja heidän pitää sen omistaman.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Vaan palatkaat te ja menkäät korpeen, Punaisen meren tietä.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Niin te vastasitte ja sanoitte minulle: me olemme rikkoneet Herraa vastaan: me menemme ja sodimme, niinkuin Herra meidän Jumalamme meille käskenyt on. Kuin te siis valmiit olitte, jokainen sota-aseinensa, ja ynseydessä menitte vuorelle,
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Sanoi Herra minulle: sano heille: ei teidän pidä sinne menemän, eikä myös sotiman, sillä en minä ole teidän kanssanne, ettette lyötäisi teidän vihollistenne edessä.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Koska minä näin teille sanoin, niin ette kuulleet minua, vaan olitte Herran sanalle vastahakoiset, ja olitte röyhkeät menemään vuorelle.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Niin läksivät Amorilaiset, jotka vuorella asuivat, teitä vastaan, ja ajoivat teitä takaa niinkuin kimalaiset tekevät, ja löivät teitä maahan Seirissä Hormaan asti.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Kuin te sieltä palasitte ja itkitte Herran edessä, niin ei Herra tahtonut kuulla teidän ääntänne, eikä korviinsa ottanut.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
Niin olette te olleet Kadeksessa kauvan aikaa, niiden päiväin luvun jälkeen, kuin te viivyitte siellä (odottain vakoojia).

< Deuteronomy 1 >