< Numbers 27 >

1 Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
Wtedy przyszły córki Selofchada, syna Chefera, syna Gileada, syna Makira, syna Manassesa, z rodu Manassesa, syna Józefa; a to są imiona jego córek: Machla, Noa, Chogla, Milka i Tirsa.
2 Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
I stanęły przed Mojżeszem, przed kapłanem Eleazarem, przed naczelnikami i całym zgromadzeniem u wejścia do Namiotu Zgromadzenia i powiedziały:
3 “Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
Nasz ojciec umarł na pustyni, ale nie należał do zgrai tych, którzy zbuntowali się przeciw PANU w gromadzie Koracha. Umarł za własny grzech, a nie miał synów.
4 Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
Dlaczego imię naszego ojca miałoby zniknąć z jego rodziny przez to, że nie miał syna? Dajcie nam posiadłość pośród braci naszego ojca.
5 Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
Mojżesz przedstawił więc ich sprawę PANU.
6 Olúwa sì wí fún un pé,
I PAN powiedział do Mojżesza:
7 “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
Córki Selofchada słusznie mówią: Daj im koniecznie dziedziczną posiadłość pośród braci ich ojca, a przenieś na nie dziedzictwo ich ojca.
8 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
I przemów do synów Izraela tak: Jeśli ktoś umrze, a nie miał syna, wtedy przeniesiecie jego dziedzictwo na jego córkę.
9 Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
A jeśli nie miał córki, to dacie jego dziedzictwo jego braciom.
10 Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
A jeśli nie miał braci, to dacie jego dziedzictwo braciom jego ojca.
11 Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
A jeśli jego ojciec nie miał braci, to dacie jego dziedzictwo najbliższemu krewnemu z jego rodziny, aby je odziedziczył. I będzie to dla synów Izraela ustawą prawną, jak PAN rozkazał Mojżeszowi.
12 Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
Potem PAN powiedział do Mojżesza: Wstąp na tę górę Abarim i spójrz na ziemię, którą dałem synom Izraela.
13 Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
A gdy ją zobaczysz, zostaniesz i ty przyłączony do swego ludu, jak został przyłączony twój brat Aaron.
14 nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
Dlatego że sprzeciwiliście się mojemu rozkazowi na pustyni Syn, podczas buntu zgromadzenia, i nie uświęciliście mnie na ich oczach u tych wód. [To są] wody Meriba w Kadesz, na pustyni Syn.
15 Mose sọ fún Olúwa wí pé,
Wtedy Mojżesz powiedział do PANA:
16 “Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
Niech PAN, Bóg duchów wszelkiego ciała, ustanowi męża nad zgromadzeniem;
17 láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
Który będzie wychodził przed nim i który będzie wchodził przed nim, który będzie je wyprowadzał i który będzie je przyprowadzał, aby zgromadzenie PANA nie było jak owce, które nie mają pasterza.
18 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
PAN powiedział do Mojżesza: Weź do siebie Jozuego, syna Nuna, męża, w którym jest [mój] Duch, i połóż na nim swoją rękę;
19 Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
I postaw go przed kapłanem Eleazarem i przed całym zgromadzeniem, i na ich oczach daj mu polecenie;
20 Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
I przenieś na niego część swojej godności, aby [go] słuchało całe zgromadzenie synów Izraela.
21 Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
Będzie on stawał przed kapłanem Eleazarem, aby ten za niego radził się przed PANEM za pośrednictwem sądu Urim. Na jego rozkaz będą wychodzić i na jego rozkaz będą wchodzić – on, a z nim wszyscy synowie Izraela, całe zgromadzenie.
22 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
I Mojżesz uczynił tak, jak PAN mu rozkazał. Wziął Jozuego i postawił go przed kapłanem Eleazarem i przed całym zgromadzeniem.
23 Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Następnie położył na niego swoje ręce i dał mu polecenie, tak jak PAN nakazał przez Mojżesza.

< Numbers 27 >