< Nahum 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
Isiqalekiso ngeNiniva. Incwadi yombono kaNahume umʼElikhoshi.
2 Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san, Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú. Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
UThixo uNkulunkulu olobukhwele lophindiselayo; uThixo uyaphindisela njalo ulolaka olukhulu. UThixo uyaphindisela ezitheni zakhe lolaka lwakhe lukhulu ezitheni zakhe.
3 Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára; Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà. Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì, ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
UThixo uyaphuza ukuthukuthela njalo ulamandla amakhulu; uThixo kayikumyekela olecala engajeziswanga. Indlela yakhe iphakathi kwesivunguzane lesiphepho, amayezi aluthuli lwezinyawo zakhe.
4 Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ; Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ. Baṣani àti Karmeli sì rọ. Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
Ukhuza ulwandle alomise; wenza yonke imifula itshe. IBhashani leKhameli kuyabuna lemiqhakazo yaseLebhanoni ibune.
5 Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́, ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀, àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Izintaba ziyanyikinyeka phambi kwakhe, lamaqaqa ayancibilika. Umhlaba uyagedezela ngobukhona bakhe, umhlaba labo bonke abahlala kuwo.
6 Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀? Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀? Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná; àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
Ngubani ongamelana lentukuthelo yakhe na? Ngubani ongalumela ulaka lwakhe oluvuthayo na? Ulaka lwakhe luthululeka njengomlilo; amadwala ayaqhekezeka phambi kwakhe.
7 Rere ni Olúwa, òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú. Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
UThixo ulungile, uyisiphephelo ezikhathini zokuhlupheka. Uyabakhathalela abathembele kuye,
8 ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin; òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
kodwa ngesikhukhula esikhulu uzatshabalalisa iNiniva; uzaxotshela izitha zakhe emnyameni.
9 Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa? Òun yóò fi òpin sí i, ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
Loba engamacebo bani abawenza ngoThixo, uzawaqeda; ukuhlupheka akuyikubuya kabili.
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
Bazathandeleka phakathi kwameva, bedakwe liwayini labo; bazaqothulwa njengenhlanga ezomileyo.
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
Wena Nineve, kuwe sekufike lowo oceba okubi ngoThixo, eluleke okubi.
12 Báyìí ni Olúwa wí: “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye, ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀, nígbà tí òun ó bá kọjá. Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
Nanku okutshiwo nguThixo: “Lanxa belababambene labo njalo bebanengi, bazaqothulwa banyamalale. Lanxa ngikuhluphile, wena Juda, kangisayikukuhlupha futhi.
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
Khathesi ngizakwephula ijogwe labo elisentanyeni yakho, ngiqamule lamaketane akho.”
14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe: “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́, Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ. Èmi yóò wa ibojì rẹ, nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
UThixo usekhuphe ilizwi ngawe Nineve elithi, “Kawuyikuba lezizukulwane ezibizwa ngebizo lakho. Ngizachitha izifanekiso ezibaziweyo lezithombe ezibunjiweyo ezisethempelini labonkulunkulu bakho. Ngizalungisa ingcwaba lakho, ngoba ungcolile.”
15 Wò ó, lórí àwọn òkè, àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá, ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà. Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́, kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́; wọn yóò sì parun pátápátá.
Khangela ezintabeni le, inyawo zalowo oletha izindaba ezinhle, omemezela ukuthula! Thakazelela imikhosi yakho we Juda, ugcwalise lezifungo zakho. Ababi kabasayikukuhlasela futhi; bazachithwa ngokupheleleyo.

< Nahum 1 >