< Micah 7 >

1 Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
Vai mie! Pentru că sunt ca după adunatul fructelor de vară, precum strugurii culeși pe urma recoltei; nu este niciun ciorchine de mâncat, sufletul meu a dorit întâiul rod copt al fructelor.
2 Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
Omul bun a pierit de pe pământ; nu este niciunul integru printre oameni; toți stau la pândă după sânge; ei vânează cu o plasă, fiecare bărbat pe fratele lui.
3 Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
Pentru ca să facă răul cu amândouă mâinile cu zel, și prințul și judecătorul cer o răsplată; și omul mare, își rostește dorința ticăloasă; astfel încheie târgul.
4 Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
Cel mai bun dintre ei este ca un mărăcine, cel mai integru este mai ascuțit decât un gard de spini; ziua paznicilor tăi și a cercetării vine; acum va fi uimirea și nedumerirea lor.
5 Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
Nu vă încredeți într-un prieten, nu vă puneți încrederea într-o călăuză; păzește-ți ușile gurii tale de cea care se întinde la pieptul tău.
6 Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
Fiindcă fiul îl dezonorează pe tată, fiica se ridică împotriva mamei sale, nora împotriva soacrei ei; dușmanii unui om sunt oamenii propriei case.
7 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
De aceea eu voi privi la DOMNUL; îl voi aștepta pe Dumnezeul salvării mele; Dumnezeul meu mă va auzi.
8 Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
Nu te bucura împotriva mea, dușmanul meu; când cad, mă voi scula; când mă așez în întuneric, DOMNUL îmi va fi o lumină.
9 Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
Voi purta indignarea DOMNULUI, fiindcă am păcătuit împotriva lui, până când va pleda în cauza mea și îmi va face judecata; mă va scoate la lumină iar eu voi privi dreptatea lui.
10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
Atunci cea care este dușmana mea va vedea, și rușinea o va acoperi pe cea care mi-a spus: Unde este DOMNUL Dumnezeul tău? Ochii mei o vor privi; acum ea va fi călcată în picioare ca noroiul de pe străzi.
11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
În ziua în care zidurile tale vor fi construite, în acea zi hotărârea va fi mult îndepărtată.
12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
În acea zi de asemenea el va veni din Asiria, până la tine, și din cetățile fortificate, și din fortăreață până la râu, și de la mare la mare, și din munte la munte.
13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
Cu toate acestea, țara va fi părăsită din cauza celor ce locuiesc în ea, datorită roadelor faptelor lor.
14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
Paște-ți poporul cu toiagul tău, turma moștenirii tale, care locuiește singură în pădure, în mijlocul Carmelului; să se hrănească în Basan și Galaad, ca în zilele din vechime.
15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
Lui îi voi arăta lucruri minunate, conform cu zilele ieșirii tale din țara Egiptului.
16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
Națiunile vor vedea și vor fi încurcate în toată tăria lor; ei [își] vor pune mâna la gură, urechile lor vor fi surde.
17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
Vor linge țărâna ca un șarpe, vor ieși din găurile lor ca viermii pământului; le va fi frică de DOMNUL, Dumnezeul nostru, și se vor înfricoșa din cauza ta.
18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
Cine este un Dumnezeu ca tine, care iartă nelegiuirea și trece cu vederea încălcarea de lege a rămășiței moștenirii sale? Nu își ține mânia pentru totdeauna, fiindcă găsește plăcere în milă.
19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
El se va întoarce din nou, va avea milă de noi; el va supune nelegiuirile noastre; și tu vei arunca toate păcatele lor în adâncurile mării.
20 Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.
Tu îi vei împlini lui Iacob adevărul și lui Avraam mila, pe care le-ai jurat părinților noștri în zilele din vechime.

< Micah 7 >